< Nombres 32 >

1 Or les enfants de Ruben et les enfants de Gad avaient des troupeaux nombreux, considérables; et ils virent le pays de Jazer et le pays de Galaad, et voici, ce lieu était un lieu propre pour le bétail.
Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
2 Et les enfants de Gad et les enfants de Ruben vinrent, et parlèrent à Moïse, à Éléazar, le sacrificateur, et aux principaux de l'assemblée, en disant:
Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
3 Ataroth, Dibon, Jazer, Nimra, Hesbon, Élealé, Sebam, Nébo et Beon,
“Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
4 Ce pays, que l'Éternel a frappé devant l'assemblée d'Israël, est un pays propre pour les troupeaux, et tes serviteurs ont des troupeaux.
Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
5 Ils dirent donc: Si nous avons trouvé grâce à tes yeux, que ce pays soit donné en possession à tes serviteurs; ne nous fais point passer le Jourdain.
Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
6 Mais Moïse répondit aux enfants de Gad et aux enfants de Ruben: Vos frères iront-ils à la guerre, tandis que vous, vous demeurerez ici?
Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
7 Pourquoi détourneriez-vous le cœur des enfants d'Israël de passer au pays que l'Éternel leur a donné?
Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
8 C'est ainsi que firent vos pères, quand je les envoyai de Kadès-Barnéa pour examiner le pays.
Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
9 Car ils montèrent jusqu'au torrent d'Eshcol, et virent le pays; et ils détournèrent le cœur des enfants d'Israël, pour ne point entrer au pays que l'Éternel leur avait donné.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
10 Et la colère de l'Éternel s'enflamma en ce jour-là, et il fit ce serment et dit:
Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
11 Les hommes qui sont montés d'Égypte, depuis l'âge de vingt ans et au-dessus, ne verront jamais le pays que j'ai juré de donner à Abraham, à Isaac et à Jacob, car ils n'ont pas pleinement marché après moi;
‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
12 Excepté Caleb, fils de Jéphunné, le Kenizien, et Josué, fils de Nun, car ils ont suivi pleinement l'Éternel.
kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
13 Ainsi la colère de l'Éternel s'enflamma contre Israël; et il les fit errer dans le désert, quarante ans, jusqu'à ce que toute la génération qui avait fait ce qui est mauvais aux yeux de l'Éternel, eût été consumée.
Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
14 Et voici, vous vous êtes levés à la place de vos pères, comme une race d'hommes pécheurs, pour augmenter encore l'ardeur de la colère de l'Éternel contre Israël.
“Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
15 Car si vous vous détournez de lui, il continuera encore à laisser ce peuple dans le désert, et vous le ferez périr tout entier.
Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
16 Mais ils s'approchèrent de Moïse, et dirent: Nous bâtirons ici des parcs pour nos troupeaux, et des villes pour nos petits enfants;
Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
17 Puis nous nous équiperons promptement pour marcher devant les enfants d'Israël, jusqu'à ce que nous les ayons fait entrer dans leur lieu; mais nos petits enfants demeureront dans les villes fortes, à cause des habitants du pays.
Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
18 Nous ne retournerons point dans nos maisons, que chacun des enfants d'Israël n'ait pris possession de son héritage;
A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
19 Et nous ne posséderons rien avec eux au delà du Jourdain ni plus loin, parce que notre héritage nous sera échu de ce côté-ci du Jourdain, à l'Orient.
A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
20 Et Moïse leur dit: Si vous faites cela, si vous vous équipez pour aller au combat devant l'Éternel,
Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
21 Et que chacun de vous passe, équipé, le Jourdain devant l'Éternel, jusqu'à ce qu'il ait chassé ses ennemis de devant lui,
Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
22 Et que le pays soit soumis devant l'Éternel; et qu'ensuite vous vous en retourniez; alors vous serez innocents envers l'Éternel et envers Israël, et ce pays vous appartiendra pour le posséder devant l'Éternel.
Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
23 Mais si vous n'agissez pas ainsi, voici, vous aurez péché contre l'Éternel, et sachez que votre péché vous trouvera.
“Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
24 Bâtissez donc des villes pour vos petits enfants, et des parcs pour vos troupeaux, et faites ce que vous avez dit.
Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
25 Alors les enfants de Gad et les enfants de Ruben parlèrent à Moïse, en disant: Tes serviteurs feront ce que mon seigneur commande.
Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
26 Nos petits enfants, nos femmes, nos troupeaux et tout notre bétail demeureront ici dans les villes de Galaad;
Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
27 Et tes serviteurs passeront, tous équipés pour la guerre, devant l'Éternel, prêts à combattre, comme mon seigneur l'a dit.
Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
28 Alors Moïse donna des ordres à leur égard à Éléazar, le sacrificateur, à Josué, fils de Nun, et aux chefs de famille des tribus des enfants d'Israël.
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
29 Et Moïse leur dit: Si les enfants de Gad et les enfants de Ruben passent avec vous le Jourdain, tous équipés pour le combat devant l'Éternel, et que le pays soit soumis devant vous, vous leur donnerez en possession le pays de Galaad;
Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
30 Mais s'ils ne passent point en armes avec vous, ils auront leur possession parmi vous au pays de Canaan.
Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
31 Et les enfants de Gad et les enfants de Ruben répondirent, en disant: Nous ferons ce que l'Éternel a dit à tes serviteurs;
Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
32 Nous passerons en armes devant l'Éternel au pays de Canaan; mais nous posséderons pour notre héritage ce qui est de ce côté-ci du Jourdain.
A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
33 Ainsi Moïse donna aux enfants de Gad et aux enfants de Ruben, et à la moitié de la tribu de Manassé, fils de Joseph, le royaume de Sihon, roi des Amoréens, et le royaume d'Og, roi de Bassan, le pays avec ses villes, avec les territoires des villes du pays tout autour.
Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
34 Alors les enfants de Gad bâtirent Dibon, Ataroth, Aroër,
Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
35 Atroth-Shophan, Jaezer, Jogbeha,
pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
36 Beth-Nimra, et Beth-Haran, villes fortes. Ils firent aussi des parcs pour leurs troupeaux.
pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
37 Et les enfants de Ruben bâtirent Hesbon, Elealé, Kirjathaïm,
Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
38 Nébo, et Baal-Meon, dont les noms furent changés, et Sibma; et ils donnèrent des noms aux villes qu'ils bâtirent.
pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
39 Or, les enfants de Makir, fils de Manassé, allèrent en Galaad, et s'en emparèrent, et dépossédèrent les Amoréens qui y étaient.
Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
40 Moïse donna donc Galaad à Makir, fils de Manassé, qui y habita.
Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
41 Et Jaïr, fils de Manassé, alla et prit leurs bourgs, et les appela bourgs de Jaïr.
Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
42 Et Nobach alla et prit Kenath avec les villes de son ressort, et l'appela Nobach d'après son nom.
Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.

< Nombres 32 >