< Josué 23 >

1 Il arriva, longtemps après que l'Éternel eut donné du repos à Israël devant tous les ennemis qui l'entouraient, que Josué, étant devenu vieux, avancé en âge,
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 Appela tout Israël, ses anciens, ses chefs, ses juges et ses officiers, et leur dit: Je suis vieux, je suis avancé en âge.
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 Et vous, vous avez vu tout ce que l'Éternel votre Dieu a fait à toutes ces nations devant vous; car c'est l'Éternel votre Dieu qui a combattu pour vous.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 Voyez, je vous ai partagé par le sort, en héritage, selon vos tribus, ces nations qui sont restées, depuis le Jourdain, et toutes les nations que j'ai exterminées, jusqu'à la grande mer, vers le soleil couchant;
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Et l'Éternel votre Dieu les chassera, et les dépossédera devant vous; et vous posséderez leur pays, comme l'Éternel votre Dieu vous l'a dit.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 Soyez donc bien fermes à observer et à faire tout ce qui est écrit dans le livre de la loi de Moïse; ne vous en détournez ni à droite ni à gauche,
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 Sans vous mêler à ces nations qui sont restées parmi vous; ne faites point mention du nom de leurs dieux; ne faites jurer personne par eux; ne les servez point et ne vous prosternez point devant eux.
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 Mais attachez-vous à l'Éternel votre Dieu, comme vous l'avez fait jusqu'à ce jour.
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 Car l'Éternel a dépossédé devant vous des nations grandes et fortes; mais quant à vous, personne jusqu'à ce jour n'a subsisté devant vous.
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 Un seul d'entre vous en poursuit mille; car l'Éternel votre Dieu est celui qui combat pour vous, comme il vous l'a dit.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Prenez donc bien garde à vous-mêmes, pour aimer l'Éternel votre Dieu.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 Car, si vous vous détournez et que vous vous attachiez au reste de ces nations qui sont demeurées parmi vous; si vous vous alliez avec elles par mariages, et que vous vous mêliez avec elles, et elles avec vous,
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 Sachez bien que l'Éternel votre Dieu ne continuera plus à déposséder ces nations devant vous; mais elles seront pour vous un filet et un piège, un fouet dans vos côtés et des épines dans vos yeux, jusqu'à ce que vous périssiez de dessus ce bon pays que l'Éternel votre Dieu vous a donné.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 Et voici, je m'en vais aujourd'hui par le chemin de toute la terre; reconnaissez donc de tout votre cœur et de toute votre âme, qu'il n'est pas tombé un seul mot de toutes les bonnes paroles que l'Éternel votre Dieu a prononcées sur vous; tout s'est accompli pour vous; il n'en est pas tombé un seul mot.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 Et comme toutes les bonnes paroles que l'Éternel votre Dieu vous avait dites vous sont arrivées, il arrivera de même que l'Éternel fera venir sur vous toutes les paroles mauvaises, jusqu'à ce qu'il vous ait exterminés de dessus ce bon pays que l'Éternel votre Dieu vous a donné.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Si vous transgressez l'alliance de l'Éternel votre Dieu, qu'il vous a commandé d'observer, si vous allez servir d'autres dieux et vous prosterner devant eux, la colère de l'Éternel s'embrasera contre vous, et vous périrez promptement de dessus ce bon pays qu'il vous a donné.
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”

< Josué 23 >