< Jérémie 40 >

1 La parole qui fut adressée par l'Éternel à Jérémie après que Nébuzar-Adan, chef des gardes, l'eut renvoyé de Rama; quand il le fit chercher, Jérémie était lié de chaînes parmi tous les captifs de Jérusalem et de Juda qu'on transportait à Babylone.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rama. Ó rí Jeremiah tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrín gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jerusalẹmu àti Juda. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli.
2 Le chef des gardes prit donc Jérémie, et lui dit: L'Éternel ton Dieu a prononcé ce mal contre ce lieu;
Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremiah, ó sọ fún un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
3 Et l'Éternel l'a fait venir, et il a fait comme il avait dit, parce que vous avez péché contre l'Éternel, et que vous n'avez point écouté sa voix; c'est pourquoi ceci vous est arrivé.
Nísinsin yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
4 Et maintenant, voici, je te délivre aujourd'hui des chaînes que tu as aux mains. S'il te plaît de venir avec moi à Babylone, viens, et j'aurai soin de toi. Mais s'il ne te plaît pas de venir avec moi à Babylone, ne le fais pas; regarde, tout le pays est à ta disposition; va où il te semblera bon et convenable d'aller.
Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lé mi ká lọ sí Babeli, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, dúró síbí. Wò ó, gbogbo orílẹ̀-èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”
5 Et comme il ne s'en retournait point: Retourne donc, dit-il, vers Guédalia, fils d'Achikam, fils de Shaphan, que le roi de Babylone a établi sur les villes de Juda, et demeure avec lui parmi le peuple; ou bien, va partout où il te conviendra d'aller. Puis le chef des gardes lui donna des vivres et des présents, et le congédia.
Ẹ̀wẹ̀, kí ó tó di pé Jeremiah pẹ̀yìndà láti máa lọ, Nebusaradani fi kún un wí pé, “Padà tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu lọ, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ìlú Juda, kí o sì máa gbé ní àárín àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o máa lọ ibikíbi tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ.” Nígbà náà ni balógun náà fún un ní oúnjẹ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
6 Jérémie alla donc vers Guédalia, fils d'Achikam, à Mitspa, et demeura avec lui au milieu du peuple qui avait été laissé de reste dans le pays.
Báyìí ni Jeremiah lọ sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ní Mispa, ó sì dúró tì í láàrín àwọn ènìyàn tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ náà.
7 Or tous les chefs des gens de guerre qui étaient dans la campagne, eux et leurs gens, apprirent que le roi de Babylone avait établi Guédalia, fils d'Achikam, gouverneur du pays, et qu'il lui avait confié les hommes, les femmes et les enfants, d'entre les plus pauvres du pays, de ceux qui n'avaient pas été transportés à Babylone.
Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn tí wọ́n kù lórí orílẹ̀-èdè náà gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀ ní ilẹ̀ náà; àti pé ó ti fi àwọn ọkùnrin, obìnrin àti ọmọdé tí wọ́n jẹ́ tálákà ní ilẹ̀ náà tí wọn kò kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì sí ìkáwọ́ rẹ̀,
8 Alors ils vinrent vers Guédalia, à Mitspa, savoir: Ismaël, fils de Néthania, Jochanan et Jonathan, fils de Karéach, et Séraja, fils de Thanhumeth, et les fils d'Ephaï, de Nétopha, et Jézania, fils du Maacathite, eux et leurs gens.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ní Mispa; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, Johanani àti Jonatani ọmọkùnrin ti Karea, Seraiah ọmọkùnrin Tanhumeti tí í ṣe ọmọkùnrin Efai ará Netofa àti Jesaniah ọmọkùnrin Maakati àti àwọn ènìyàn wọn.
9 Et Guédalia, fils d'Achikam, fils de Shaphan, leur jura, à eux et à leurs gens, et leur dit: Ne craignez pas de servir les Caldéens; demeurez dans le pays, et servez le roi de Babylone; et vous vous en trouverez bien.
Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu, ọmọkùnrin ti Ṣafani ṣe ìbúra láti tún fi dá àwọn ènìyàn lójú pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù láti sin àwọn Babeli.” Ó sọ wí pé, “Gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì máa sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.
10 Et pour moi, voici, je demeurerai à Mitspa, pour être aux ordres des Caldéens qui viendront vers nous. Mais vous, recueillez le vin, les fruits d'été et l'huile, mettez-les dans vos vases, et demeurez dans les villes que vous occupez.
Èmi fúnra mi yóò dúró ní Mispa láti ṣojú yín níwájú Babeli tí wọ́n tọ̀ wá wá. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni yóò máa kórè ọtí wáìnì, èso igi àti òróró; kí ẹ sì kó wọn sí inú àpò àpamọ́wọ́ yín; kí ẹ̀yin sì máa gbé ní ìlú tí ẹ ti gbà.”
11 Tous les Juifs aussi qui étaient au pays de Moab, chez les enfants d'Ammon et dans l'Idumée, et dans toutes ces contrées, ayant appris que le roi de Babylone avait laissé quelque reste en Juda, et qu'il leur avait donné pour gouverneur Guédalia, fils d'Achikam, fils de Shaphan,
Nígbà tí gbogbo àwọn Juda ní Moabu, Ammoni, Edomu àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ pé ọba Babeli ti fi ohun tókù sílẹ̀ ní Juda, àti pé ó ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ọmọkùnrin Ṣafani gẹ́gẹ́ bí gómìnà lórí wọn.
12 Tous ces Juifs revinrent de tous les lieux où ils avaient été chassés, et se rendirent dans le pays de Juda, vers Guédalia, à Mitspa; et ils recueillirent du vin et des fruits d'été en grande abondance.
Gbogbo wọn padà wá sí ilẹ̀ Juda sọ́dọ̀ Gedaliah ní Mispa láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí a ti lé wọn sí. Wọ́n sì kórè ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọtí wáìnì àti èso igi.
13 Mais Jochanan, fils de Karéach, et tous les chefs des troupes qui étaient dans la campagne, vinrent vers Guédalia, à Mitspa,
Johanani ọmọkùnrin ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí ó kù ní orílẹ̀-èdè sì tọ Gedaliah wá ní Mispa.
14 Et lui dirent: Sais-tu bien que Baalis, roi des enfants d'Ammon, a envoyé Ismaël, fils de Néthania, pour t'ôter la vie? Mais Guédalia, fils d'Achikam, ne les crut point.
Wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ha mọ̀ pé Baalisi ọba àwọn Ammoni ti rán Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah láti lọ mú ẹ̀mí rẹ?” Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọkùnrin ti Ahikamu kò gbà wọ́n gbọ́.
15 Alors Jochanan, fils de Karéach, dit secrètement à Guédalia, à Mitspa: Laisse-moi aller et frapper Ismaël, fils de Néthania, sans que personne le sache. Pourquoi t'ôterait-il la vie? Pourquoi tous les Juifs qui se sont rassemblés vers toi, seraient-ils dispersés, et le reste de Juda périrait-il?
Nígbà náà ni Johanani ọmọkùnrin Karea sọ ní ìkọ̀kọ̀ fún Gedaliah ní Mispa pé, “Jẹ́ kí èmi lọ pa Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ èyí. Kí ni ìdí rẹ̀ tí yóò ṣe mú ẹ̀mí rẹ, tí o sì ṣe fẹ́ mú àwọn Júù tí ó yí ọ ká túká, kí ìyókù Juda sì parun?”
16 Mais Guédalia, fils d'Achikam, répondit à Jochanan, fils de Karéach: Ne fais pas cela, car ce que tu dis d'Ismaël est faux.
Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọ Ahikamu sọ fún Johanani ọmọ Karea pé, “Má ṣe ṣe nǹkan yìí! Nítorí nǹkan tí ò ń sọ nípa Iṣmaeli kì í ṣe òtítọ́.”

< Jérémie 40 >