< Ézéchiel 17 >
1 La parole de l'Éternel me fut encore adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
2 Fils de l'homme, propose une énigme, présente une parabole à la maison d'Israël.
“Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
3 Tu diras: Ainsi a dit le Seigneur, l'Éternel: Un grand aigle, aux grandes ailes, aux ailes étendues, tout couvert d'un duvet de couleurs variées, vint sur le Liban et enleva la cime d'un cèdre.
Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
4 Il arracha le plus élevé de ses rameaux, le transporta en un pays marchand, et le déposa dans une ville de commerce.
ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
5 Il prit ensuite du plant du pays et le confia à un sol fertile; il le plaça près des eaux abondantes et le planta comme un saule.
“‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
6 Le plant poussa, devint un cep de vigne étendu, mais peu élevé; ses rameaux étaient tournés du côté de l'aigle, et ses racines étaient sous lui; il devint un cep, produisit des sarments et donna du feuillage.
Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
7 Mais il y avait un autre grand aigle, aux grandes ailes, au plumage épais; et voici, des couches où il était planté, le cep étendit vers lui ses racines, et dirigea ses rameaux de son côté, afin qu'il l'arrosât.
“‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
8 Et pourtant il était planté dans un bon terrain, près d'eaux abondantes, de manière à produire des sarments, à porter du fruit et à devenir un cep superbe.
Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
9 Dis: Ainsi a dit le Seigneur, l'Éternel: Le cep réussira-t-il? Le premier aigle n'en arrachera-t-il pas les racines, et n'en coupera-t-il pas les fruits, de manière à faire sécher tous les rejetons qu'il aura produits? Il séchera, et il n'y aura besoin ni d'un grand effort, ni de beaucoup de gens pour le séparer de ses racines.
“Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
10 Voici, il est planté; mais réussira-t-il? Dès que le vent d'orient le touchera, ne séchera-t-il pas entièrement? Il séchera sur les couches où il a été planté.
Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
11 Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces termes:
Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
12 Dis à cette maison rebelle: Ne savez-vous pas ce que signifient ces choses? Dis: Voici, le roi de Babylone est allé à Jérusalem; il a pris le roi et les principaux, et les a emmenés avec lui à Babylone.
“Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 Et il a pris un rejeton de la race royale, il a fait alliance avec lui et lui a fait prêter serment; et il s'est emparé des puissants du pays,
Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
14 Afin que le royaume fût tenu dans l'abaissement, sans pouvoir s'élever, tout en le laissant subsister, s'il observait son alliance.
Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
15 Mais il s'est révolté contre lui, en envoyant des ambassadeurs en Égypte, afin qu'on lui donnât des chevaux et un grand nombre d'hommes. Pourra-t-il réussir, échapper, celui qui a fait de telles choses? Il a rompu l'alliance, et il échapperait!
Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
16 Je suis vivant! dit le Seigneur, l'Éternel, c'est dans la résidence du roi qui l'a fait régner, dont il a méprisé le serment et rompu l'alliance, c'est près de lui, au milieu de Babylone, qu'il mourra!
“‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
17 Et Pharaon, avec une grande armée et des troupes nombreuses, ne fera rien pour lui dans la guerre, quand on aura élevé des remparts et construit des tours pour faire périr nombre d'âmes.
Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
18 Car il a méprisé le serment, en violant l'alliance; et voici, après avoir donné sa main, il a néanmoins fait toutes ces choses. Il n'échappera pas!
Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
19 C'est pourquoi, ainsi a dit le Seigneur, l'Éternel: Je suis vivant! c'est mon serment qu'il a méprisé, mon alliance qu'il a rompue; je ferai retomber cela sur sa tête.
“‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
20 J'étendrai mon rets sur lui, et il sera pris dans mes filets; je l'emmènerai à Babylone où je plaiderai contre lui sur sa perfidie à mon égard.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
21 Et tous les fuyards de toutes ses troupes tomberont par l'épée; et ceux qui resteront seront dispersés à tous les vents. Et vous saurez que c'est moi, l'Éternel, qui ai parlé.
Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
22 Ainsi a dit le Seigneur, l'Éternel: Je prendrai moi-même la cime d'un cèdre élevé, et je la planterai. De l'extrémité de ses rameaux, je couperai un tendre rejeton, et moi-même je le planterai sur une montagne haute et élevée.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
23 Sur la haute montagne d'Israël, je le planterai; il poussera des jets, et produira des fruits; il deviendra un cèdre magnifique, et des oiseaux de toute espèce viendront s'abriter sous lui; tout ce qui a des ailes habitera à l'ombre de ses rameaux.
Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
24 Et tous les arbres des champs connaîtront que, moi l'Éternel, j'ai abaissé l'arbre élevé, et élevé le petit arbre, que j'ai fait sécher l'arbre vert et fait reverdir l'arbre sec. Moi l'Éternel, je l'ai dit, et je le ferai.
Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”