< Deutéronome 17 >

1 Tu ne sacrifieras à l'Éternel ton Dieu, ni taureau, ni agneau ni chevreau qui ait un défaut, un vice d'aucune espèce; car c'est une abomination pour l'Éternel ton Dieu.
Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
2 Quand il se trouvera au milieu de toi, dans quelqu'une des villes que l'Éternel ton Dieu te donne, un homme ou une femme qui fasse ce qui est mauvais aux yeux de l'Éternel ton Dieu, en transgressant son alliance,
Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
3 Et qui aille et serve d'autres dieux, et qui se prosterne devant eux, devant le soleil, ou devant la lune, ou devant toute l'armée des cieux, ce que je n'ai pas commandé;
èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
4 Et que cela t'aura été rapporté, et que tu l'auras appris; alors tu t'informeras exactement, et si tu trouves que ce qu'on a dit soit véritable et certain, et que cette abomination ait eté commise en Israël,
tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
5 Tu feras sortir vers tes portes cet homme, ou cette femme, qui aura fait cette méchante action, soit l'homme, soit la femme, et tu les lapideras, et ils mourront.
Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
6 C'est sur la parole de deux ou trois témoins que sera mis à mort celui qui devra mourir; il ne sera pas mis à mort sur la parole d'un seul témoin.
Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
7 La main des témoins sera la première sur lui pour le faire mourir, et ensuite la main de tout le peuple. Tu ôteras ainsi le méchant du milieu de toi.
Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
8 Quand une affaire sera trop difficile à juger pour toi, qu'il faille distinguer entre sang et sang, entre cause et cause, entre plaie et plaie, objets de contestation dans tes portes, tu te lèveras et tu monteras au lieu que l'Éternel ton Dieu aura choisi;
Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
9 Et tu viendras aux sacrificateurs de la race de Lévi, et au juge qui sera en ce temps-là, et tu les consulteras, et ils te déclareront ce que porte le droit.
Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
10 Et tu agiras conformément à ce qu'ils t'auront déclaré, du lieu que l'Éternel aura choisi, et tu prendras garde à faire selon tout ce qu'ils t'auront enseigné.
Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
11 Tu agiras conformément à la loi qu'ils t'auront enseignée, et selon le droit qu'ils t'auront prononcé; tu ne te détourneras point de ce qu'ils t'auront déclaré, ni à droite ni à gauche.
Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
12 Mais l'homme qui agira avec orgueil et ne voudra point obéir au sacrificateur qui se tient là pour servir l'Éternel ton Dieu, ou au juge, cet homme-là mourra, et tu ôteras le méchant d'Israël;
Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
13 Et tout le peuple l'entendra et craindra, et ils ne s'élèveront plus par orgueil.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
14 Quand tu seras entré au pays que l'Éternel ton Dieu te donne, et que tu le posséderas et y demeureras, si tu dis: J'établirai un roi sur moi, comme toutes les nations qui m'entourent,
Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
15 Tu ne manqueras pas de t'établir pour roi celui que l'Éternel ton Dieu aura choisi; tu établiras sur toi un roi d'entre tes frères; tu ne pourras point mettre sur toi un homme étranger, qui ne soit point ton frère.
Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
16 Seulement il ne se procurera point un grand nombre de chevaux, et il ne ramènera point le peuple en Égypte, afin d'augmenter le nombre des chevaux; car l'Éternel vous a dit: Vous ne retournerez plus par ce chemin-là.
Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
17 Il ne prendra pas non plus un grand nombre de femmes, de peur que son cœur ne se détourne; il ne s'amassera pas non plus beaucoup d'argent et d'or.
Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
18 Et dès qu'il sera assis sur son trône royal, il écrira pour lui dans un livre, un double de cette loi, qu'il recevra des sacrificateurs de la race de Lévi.
Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
19 Et ce livre sera avec lui, et il y lira tous les jours de sa vie, afin qu'il apprenne à craindre l'Éternel son Dieu, à prendre garde à toutes les paroles de cette loi et à ces statuts pour les pratiquer;
Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
20 De peur que son cœur ne s'élève au-dessus de ses frères et qu'il ne se détourne de ce commandement, à droite ou à gauche; et afin qu'il prolonge ses jours dans son règne, lui et ses fils, au milieu d'Israël.
Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.

< Deutéronome 17 >