< 2 Chroniques 22 >
1 Les habitants de Jérusalem établirent pour roi à sa place Achazia, le plus jeune de ses fils, parce que les troupes qui étaient venues au camp avec les Arabes, avaient tué tous les plus âgés; et Achazia, fils de Joram, roi de Juda, régna.
Àwọn ènìyàn Jerusalẹmu mú Ahasiah, ọmọ Jehoramu tí ó kéré jùlọ, jẹ ọba ní ipò rẹ̀, láti ìgbà tí àwọn onísùnmọ̀mí, tí ó wá pẹ̀lú àwọn ará Arabia sínú ibùdó, tí wọn sì ti pa àwọn ọmọkùnrin àgbà. Bẹ́ẹ̀ ni Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
2 Achazia était âgé de quarante-deux ans, quand il devint roi, et il régna un an à Jérusalem. Sa mère s'appelait Athalie, fille d'Omri.
Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún kan. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Ataliah, ọmọ ọmọbìnrin Omri.
3 Il suivit aussi les voies de la maison d'Achab; car sa mère était sa conseillère pour faire du mal.
Ó mú ìrìn ní ọ̀nà ilé Ahabu. Nítorí tí ìyá rẹ̀ kì í láyà nínú ṣíṣe búburú.
4 Il fit donc ce qui est mauvais aux yeux de l'Éternel, comme la maison d'Achab; parce qu'ils furent ses conseillers après la mort de son père, pour sa ruine.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí lẹ́yìn ikú baba a rẹ̀, wọ́n di olùgbani nímọ̀ràn rẹ̀ sí ṣíṣe rẹ̀.
5 Gouverné par leurs conseils, il alla même avec Joram, fils d'Achab, roi d'Israël, à la guerre, à Ramoth de Galaad, contre Hazaël, roi de Syrie. Et les Syriens frappèrent Joram,
Ó tẹ̀lé ìgbìmọ̀ wọn nígbà tí ó lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli láti gbógun ti Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Aramu ṣá Joramu ní ọgbẹ́;
6 Qui s'en retourna pour se faire guérir à Jizréel, des blessures que les Syriens lui avaient faites à Rama, lorsqu'il faisait la guerre contre Hazaël, roi de Syrie. Alors Azaria, fils de Joram, roi de Juda, descendit pour voir Joram, le fils d'Achab, à Jizréel, parce qu'il était malade.
bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí wọ́n ti dá sí i lára ní Rama ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Siria. Nígbà náà, Ahasiah, ọmọ Jehoramu ọba Juda lọ sí Jesreeli láti lọ rí Joramu ọmọ Ahabu nítorí a ti ṣá a lọ́gbẹ́.
7 Or ce fut pour son entière ruine, qui procédait de Dieu, qu'Achazia vint auprès de Joram. En effet, quand il fut arrivé, il sortit avec Joram au-devant de Jéhu, fils de Nimshi, que l'Éternel avait oint pour exterminer la maison d'Achab.
Ní gbogbo ìgbà ìbẹ̀wò Ahasiah sí Joramu, Ọlọ́run mú ìṣubú Ahasiah wá. Nígbà tí Ahasiah dé, ó jáde lọ pẹ̀lú Jehoramu láti lọ bá Jehu ọmọ Nimṣi, ẹni tí Olúwa ti fi àmì òróró yàn láti pa ìdílé Ahabu run.
8 Et il arriva, comme Jéhu faisait justice de la maison d'Achab, qu'il trouva les chefs de Juda et les fils des frères d'Achazia, qui servaient Achazia, et il les tua.
Nígbà tí Jehu ń ṣe ìdájọ́ lórí ilé Ahabu, ó rí àwọn ọmọbìnrin ọba ti Juda àti àwọn ọmọkùnrin ìbátan Ahasi, tí ó ń tọ́jú Ahasiah, ó sì pa wọ́n.
9 Il chercha ensuite Achazia, qui s'était caché à Samarie; on le prit, et on l'amena vers Jéhu, et on le fit mourir. Puis on l'ensevelit, car on dit: C'est le fils de Josaphat, qui a recherché l'Éternel de tout son cœur. Et il n'y eut plus personne dans la maison d'Achazia qui fût capable de régner.
Ó lọ láti wá Ahasiah, àti àwọn ọkùnrin rẹ̀. Àwọn arákùnrin rẹ̀ ṣẹ́gun rẹ̀ nígbà tí ó sá pamọ́ ní Samaria. A gbé e wá sí ọ̀dọ̀ Jehu, a sì pa á. Wọ́n sin ín nítorí wọ́n wí pé, “Ọmọkùnrin Jehoṣafati ni, ẹni tí ó wá Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan ní ilé Ahasiah tí ó lágbára láti gbé ìjọba náà dúró.
10 Or Athalie, mère d'Achazia, voyant que son fils était mort, se leva, et extermina toute la race royale de la maison de Juda.
Nígbà tí Ataliah ìyá Ahasiah rí i wí pé ọmọkùnrin rẹ̀ ti kú, ó tẹ̀síwájú láti pa gbogbo ìdílé ọba ti ilẹ̀ Juda run.
11 Mais Joshabath, fille du roi Joram, prit Joas, fils d'Achazia, le déroba d'entre les fils du roi qu'on faisait mourir, et le mit avec sa nourrice, dans la salle des lits. Ainsi Joshabath, fille du roi Joram et femme de Jéhojada, le sacrificateur, étant la sœur d'Achazia, le cacha aux yeux d'Athalie, qui ne le fit point mourir.
Ṣùgbọ́n Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu mú Joaṣi, ọmọkùnrin Ahasiah ó sì jí gbé lọ kúrò láàrín àwọn ọmọbìnrin ọba, àwọn tí ó kù díẹ̀ kí wọn pa. Wọn gbé òun àti olùtọ́jú rẹ̀ sínú ìyẹ̀wù. Nítorí Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu àti ìyàwó àlùfáà Jehoiada jẹ́ arábìnrin Ahasiah. Ó fi ọmọ náà pamọ́ kúrò fún Ataliah, kí ó má ba à pa á.
12 Il fut ainsi caché avec eux, six ans, dans la maison de Dieu; et Athalie régnait sur le pays.
Ó wà ní ìpamọ́ pẹ̀lú wọn ni ilé Ọlọ́run fún ọdún mẹ́fà nígbà tí Ataliah ṣàkóso ilẹ̀ náà.