< 1 Samuel 30 >

1 Or, quand David et ses gens arrivèrent à Tsiklag, le troisième jour, les Amalécites s'étaient jetés sur la contrée du midi et sur Tsiklag; ils avaient pris Tsiklag et l'avaient brûlée.
Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
2 Et ils avaient fait prisonnières les femmes qui s'y trouvaient, et les petits et les grands; ils n'avaient tué personne, mais ils les avaient emmenés, et s'étaient remis en chemin.
Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
3 David et ses gens revinrent donc à la ville; et voici, elle était brûlée; et leurs femmes, leurs fils et leurs filles, avaient été faits prisonniers.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
4 Alors David et le peuple qui était avec lui élevèrent la voix, et pleurèrent jusqu'à ce qu'il n'y eût plus en eux de force pour pleurer.
Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
5 Or les deux femmes de David avaient aussi été faites prisonnières, savoir, Achinoam, de Jizréel, et Abigaïl, de Carmel, femme de Nabal.
A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
6 Et David fut dans une grande détresse, car le peuple parlait de le lapider. Car tout le peuple avait l'âme pleine d'amertume, chacun à cause de ses fils et de ses filles; mais, David se fortifia en l'Éternel son Dieu,
Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
7 Et il dit à Abiathar, le sacrificateur, fils d'Achimélec: Apporte-moi, je te prie, l'éphod; et Abiathar apporta l'éphod à David.
Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
8 Alors David consulta l'Éternel, en disant: Poursuivrai-je cette troupe? l'atteindrai-je? Et il lui répondit: Poursuis; car certainement tu atteindras et tu délivreras.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
9 David s'en alla donc, avec les six cents hommes qui étaient avec lui; et ils arrivèrent jusqu'au torrent de Bésor, où s'arrêtèrent ceux qui demeuraient en arrière.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
10 Ainsi David et quatre cents hommes firent la poursuite; deux cents s'arrêtèrent, trop fatigués pour passer le torrent de Bésor.
Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
11 Or, ils trouvèrent dans les champs, un homme égyptien qu'ils amenèrent à David, et ils lui donnèrent du pain, qu'il mangea, et de l'eau à boire;
Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
12 Ils lui donnèrent aussi quelques figues sèches, et deux grappes de raisins secs. Il les mangea donc, et reprit ses esprits; car il n'avait point mangé de pain, ni bu d'eau depuis trois jours et trois nuits.
Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
13 Et David lui dit: A qui es-tu, et d'où es-tu? Et il répondit: Je suis un garçon égyptien, serviteur d'un homme amalécite; et mon maître m'a abandonné, parce que je tombai malade, il y a trois jours.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
14 Nous avons fait irruption au midi des Kéréthiens, et sur ce qui appartient à Juda, et au midi de Caleb, et nous avons brûlé Tsiklag.
Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
15 Alors David lui dit: Me conduiras-tu vers cette troupe? Et il répondit: Jure-moi, par le nom de Dieu, que tu ne me feras point mourir, et que tu ne me livreras point entre les mains de mon maître, et je te conduirai vers cette troupe.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
16 Et il le conduisit; et voici, ils étaient dispersés sur toute la contrée, mangeant, buvant et dansant, à cause du grand butin qu'ils avaient enlevé au pays des Philistins et au pays de Juda.
Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
17 Et David les battit, depuis l'aube du jour jusqu'au soir du lendemain; et il n'en échappa aucun, excepté quatre cents jeunes hommes qui montèrent sur des chameaux et s'enfuirent.
Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
18 Et David recouvra tout ce que les Amalécites avaient pris; il recouvra aussi ses deux femmes.
Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
19 Et il ne leur manqua personne, ni petit, ni grand, ni fils, ni filles, ni rien du butin et de tout ce qu'ils leur avaient emporté; David ramena le tout.
Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
20 David reprit aussi tout le gros et le menu bétail; et ses gens marchaient à la tête de ce troupeau et disaient: C'est ici le butin de David.
Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
21 Puis David vint vers les deux cents hommes qui avaient été trop fatigués pour suivre David, et qu'il avait fait rester au torrent de Bésor. Et ils sortirent au-devant de David, et au-devant du peuple qui était avec lui. Et David, s'approchant d'eux, leur demanda comment ils se portaient.
Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
22 Mais tous les hommes méchants et mauvais, d'entre ceux qui étaient allés avec David, prirent la parole et dirent: Puisqu'ils ne sont point venus avec nous, nous ne leur donnerons rien du butin que nous avons recouvré, sinon à chacun sa femme et ses enfants; qu'ils les emmènent, et s'en aillent.
Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
23 Mais David dit: Ce n'est pas ainsi, mes frères, que vous disposerez de ce que l'Éternel nous a donné, puisqu'il nous a gardés, et a livré entre nos mains la troupe qui était venue contre nous.
Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
24 Qui vous écouterait dans cette affaire? Car la part de celui qui descend au combat et la part de celui qui demeure au bagage, doivent être égales; ils partageront ensemble.
Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
25 Or cela s'est pratiqué depuis ce jour-là, et on en a fait une règle et un usage en Israël, jusqu'à ce jour.
Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
26 David revint donc à Tsiklag, et envoya du butin aux anciens de Juda, à ses amis, en disant: Voici un présent, pour vous, du butin des ennemis de l'Éternel.
Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
27 Il en envoya à ceux qui étaient à Béthel, à ceux qui étaient à Ramoth du Midi, à ceux qui étaient à Jatthir,
Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
28 A ceux qui étaient à Aroër, à ceux qui étaient à Siphmoth, à ceux qui étaient à Eshthémoa,
Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
29 A ceux qui étaient à Racal, et à ceux qui étaient dans les villes des Jérachméeliens, à ceux qui étaient dans les villes des Kéniens,
Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
30 A ceux qui étaient à Horma, à ceux qui étaient à Cor-Ashan, à ceux qui étaient à Athac,
àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
31 Et à ceux qui étaient à Hébron, et dans tous les lieux où David avait passé, lui et ses gens.
Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.

< 1 Samuel 30 >