< Zacharie 10 >
1 Demandez de la pluie à l'Eternel au temps de la pluie de la dernière saison, et l'Eternel fera des éclairs, et vous donnera une pluie abondante, et à chacun de l'herbe dans son champ.
Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
2 Car les Théraphims ont dit fausseté, et les devins ont vu le mensonge, ils ont proféré des songes vains, et ont donné des consolations vaines; c'est pourquoi on s'en est allé comme des brebis, et on a été abattu, parce qu'[il] n'y avait point de pasteur.
Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
3 Ma colère s'est embrasée contre ces pasteurs-là, et j'ai puni ces boucs; mais l'Eternel des armées a fait la revue de son troupeau, [savoir], de la maison de Juda; et il les a rangés en bataille comme son cheval d'honneur.
“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
4 De lui est l'encoignure, de lui est le clou, de lui est l'arc de bataille, et pareillement de lui sortira tout exacteur.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
5 Mais ils seront comme des vaillants hommes qui foulent la boue des chemins dans la bataille, et ils combattront, parce que l'Eternel sera avec eux, et les gens de cheval seront confus.
Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
6 Car je renforcerai la maison de Juda, et je préserverai la maison de Joseph; et je les ramènerai, et les ferai habiter en repos, parce que j'aurai compassion d'eux, et ils seront comme si je ne les avais point rejetés; car je suis l'Eternel leur Dieu, et je les exaucerai.
“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
7 Et ceux d'Ephraïm seront comme un vaillant homme, et leur cœur se réjouira comme par le vin; et ses fils le verront, et se réjouiront; leur cœur s'égayera en l'Eternel.
Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
8 Je leur sifflerai, et je les rassemblerai, parce que je les aurai rachetés; et ils seront multipliés comme ils l'ont été [auparavant].
Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
9 Et après que je les aurai semés entre les peuples, ils se souviendront de moi dans les pays éloignés, et ils vivront avec leurs fils, et retourneront.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
10 Ainsi je les ramènerai du pays d'Egypte, je les rassemblerai d'Assyrie, je les ferai venir au pays de Galaad, et au Liban, et il n'y aura point [assez d'espace] pour eux.
Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
11 Et la détresse passera par la mer, et il y frappera les flots; et toutes les profondeurs du fleuve seront taries, et l'orgueil de l'Assyrie sera abattu, et le sceptre d'Egypte sera ôté.
Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
12 Et je les renforcerai en l'Eternel, et ils marcheront en son Nom, dit l'Eternel.
Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.