< Psaumes 79 >

1 Psaume d'Asaph. Ô Dieu! les nations sont entrées dans ton héritage; on a profané le Temple de ta Sainteté, on a mis Jérusalem en monceaux de pierres.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
2 On a donné les corps morts de tes serviteurs pour viande aux oiseaux des cieux, [et] la chair de tes bien-aimés aux bêtes de la terre.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
3 On a répandu leur sang comme de l'eau à l'entour de Jérusalem, et il n'y avait personne qui les ensevelît.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4 Nous avons été en opprobre à nos voisins, en moquerie et en raillerie à ceux qui habitent autour de nous.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
5 Jusques à quand, ô Eternel, te courrouceras-tu à jamais? Ta jalousie s'embrasera-t-elle comme un feu?
Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
6 Répands ta fureur sur les nations qui ne te connaissent point, et sur les Royaumes qui n'invoquent point ton Nom.
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
7 Car on a dévoré Jacob, et on a ravagé ses demeures.
nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
8 Ne rappelle point devant nous les iniquités commises ci-devant; [et] que tes compassions nous préviennent; car nous sommes devenus fort chétifs.
Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
9 Ô Dieu de notre délivrance, aide-nous pour l'amour de la gloire de ton Nom, et nous délivre; et pardonne-nous nos péchés pour l'amour de ton Nom.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
10 Pourquoi diraient les nations: Où est leur Dieu? Que la vengeance du sang de tes serviteurs, qui a été répandu, soit manifestée parmi les nations en notre présence.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
11 Que le gémissement des prisonniers vienne en ta présence, [mais] réserve, selon la grandeur de ta puissance, ceux qui sont déjà voués à la mort.
Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
12 Et rends à nos voisins, dans leur sein, sept fois au double l'opprobre qu'ils t'ont fait, ô Eternel!
San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
13 Mais nous, ton peuple, et le troupeau de ta pâture, nous te célébrerons à toujours d'âge en âge, et nous raconterons ta louange.
Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.

< Psaumes 79 >