< Psaumes 52 >

1 Maskil de David, donné au maître chantre. Sur ce que Doëg Iduméen vint à Saül, et lui rapporta, disant: David est venu en la maison d'Ahimélec. Pourquoi te vantes-tu du mal, vaillant homme? La gratuité du [Dieu] Fort dure tous les jours.
Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
2 Ta langue trame des méchancetés, elle est comme un rasoir affilé, qui trompe.
Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
3 Tu aimes plus le mal que le bien, [et] le mensonge plus que de dire la vérité; (Sélah)
Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
4 Tu aimes tous les discours pernicieux, [et] le langage trompeur.
Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
5 Aussi le [Dieu] Fort te détruira pour jamais; il t'enlèvera et t'arrachera de [ta] tente, et il te déracinera de la terre des vivants; (Sélah)
Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
6 Et les justes [le] verront, et craindront, et ils se riront d'un tel homme, [disant]:
Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
7 Voilà cet homme qui ne tenait point Dieu pour sa force, mais qui s'assurait sur ses grandes richesses, et qui mettait sa force en sa malice.
“Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
8 Mais moi, je serai dans la maison de Dieu comme un olivier qui verdit. Je m'assure en la gratuité de Dieu pour toujours et à perpétuité.
Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
9 Je te célébrerai à jamais de ce que tu auras fait ces choses; et je mettrai mon espérance en ton Nom, parce qu'il est bon envers tes bien-aimés.
Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

< Psaumes 52 >