< Psaumes 45 >

1 Maskil des enfants de Coré, [qui est] un Cantique nuptial, [donné] au maitre chantre, [pour le chanter] sur Sosannim. Mon cœur médite un excellent discours, [et] j'ai dit: mes ouvrages seront pour le Roi; ma langue sera la plume d'un écrivain diligent.
Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó. Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
2 Tu es plus beau qu'aucun des fils des hommes; la grâce est répandue sur tes lèvres, parce que Dieu t'a béni éternellement.
Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
3 Ô Très-puissant, ceins ton épée sur ta cuisse, ta majesté et ta magnificence.
Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
4 Et prospère en ta magnificence; sois porté sur la parole de vérité, de débonnaireté, et de justice; et ta droite t'enseignera des choses terribles.
Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́; jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
5 Tes flèches sont aiguës, les peuples tomberont sous toi; [elles entreront] dans le cœur des ennemis du Roi.
Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
6 Ton trône, ô Dieu! est à toujours et à perpétuité; le sceptre de ton règne est un sceptre d'équité.
Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ, ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
7 Tu aimes la justice, et tu hais la méchanceté; c'est pourquoi, ô Dieu! ton Dieu t'a oint d'une huile de joie par-dessus tes compagnons.
Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ, nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
8 Ce n'est que myrrhe, aloès et casse de tous tes vêtements, [quand tu sors] des palais d'ivoire, dont ils t'ont réjoui.
Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
9 Des filles de Rois sont entre tes dames d'honneur; ta femme est à ta droite, parée d'or d'Ophir.
Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà Ofiri.
10 Ecoute fille, et considère; rends-toi attentive, oublie ton peuple, et la maison de ton père.
Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
11 Et le Roi mettra son affection en ta beauté; puisqu'il est ton Seigneur, prosterne-toi devant lui.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi nítorí òun ni olúwa rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
12 Et la fille de Tyr, [et] les plus riches des peuples te supplieront avec des présents.
Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
13 La fille du Roi est intérieurement toute pleine de gloire; son vêtement est semé d'enchâssures d'or.
Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀, iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
14 Elle sera présentée au Roi en vêtements de broderie; et les filles qui viennent après elle, et qui sont ses compagnes, seront amenées vers toi.
Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá, àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
15 Elles te seront présentées avec réjouissance et allégresse, [et] elles entreront au palais du Roi.
Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.
16 Tes enfants seront au lieu de tes pères; tu les établiras pour Princes par toute la terre.
Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
17 Je rendrai ton Nom mémorable dans tous les âges, et à cause de cela les peuples te célébreront à toujours et à perpétuité.
Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.

< Psaumes 45 >