< Psaumes 20 >
1 Psaume de David, [donné] au maître chantre. Que l'Eternel te réponde au jour que tu seras en détresse; que le nom du Dieu de Jacob te mette en une haute retraite.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
2 Qu'il envoie ton secours du saint lieu, et qu'il te soutienne de Sion.
Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
3 Qu'il se souvienne de toutes tes oblations, qu'il réduise en cendre ton holocauste; (Sélah)
Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
4 Qu'il te donne ce que ton cœur désire, et qu'il fasse réussir tes desseins.
Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
5 Nous triompherons de ta délivrance, et nous marcherons à enseignes déployées au Nom de notre Dieu; l'Eternel t'accordera toutes tes demandes.
Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
6 Déjà je connais que l'Eternel a délivré son Oint; il lui répondra des Cieux de sa Sainteté; la délivrance faite par sa droite est avec force.
Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Les uns [se vantent] de leurs chariots, et les autres de leurs chevaux, mais nous nous glorifierons du Nom de l'Eternel notre Dieu.
Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
8 Ceux-là ont ployé, et sont tombés; mais nous nous sommes relevés, et soutenus.
Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
9 Eternel, délivre. Que le Roi nous réponde au jour que nous crierons.
Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!