< Psaumes 140 >

1 Psaume de David, [donné] au maître chantre. Eternel, délivre-moi de l'homme méchant; garde-moi de l'homme violent.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
2 Ils ont pensé des maux en [leur] cœur; ils assemblent tous les jours des combats.
ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
3 Ils affilent leur langue comme un serpent; il y a du venin de vipères sous leurs lèvres; (Sélah)
Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
4 Eternel, garde-moi des mains du méchant, préserve-moi de l'homme violent, de ceux qui ont machiné de me heurter pour me faire tomber.
Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
5 Les orgueilleux m'ont caché le piège, et ils ont tendu [avec] des cordes un rets à l'endroit de mon passage, ils ont mis des trébuchets [pour me prendre]; (Sélah)
Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
6 J'ai dit à l'Eternel: tu es mon [Dieu] Fort; Eternel! prête l'oreille à la voix de mes supplications.
Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 Ô Eternel! Seigneur! la force de mon salut, tu as couvert de toutes parts ma tête au jour de la bataille.
Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
8 Eternel n'accorde point au méchant ses souhaits; ne fais point que sa pensée ait son effet, ils s'élèveraient. (Sélah)
Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
9 Quant aux principaux de ceux qui m'assiégent, que la peine de leurs lèvres les couvre.
Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Que des charbons embrasés tombent sur eux, qu'il les fasse tomber au feu, et dans des fosses profondes, sans qu'ils se relèvent.
A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
11 Que l'homme médisant ne soit point affermi en la terre; [et] quant à l'homme violent et mauvais, qu'on chasse après lui jusqu’à ce qu'il soit exterminé.
Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
12 Je sais que l'Eternel fera justice à l'affligé, [et] droit aux misérables.
Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
13 Quoi qu'il en soit, les justes célébreront ton Nom, [et] les hommes droits habiteront devant ta face.
Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.

< Psaumes 140 >