< Psaumes 136 >
1 Célébrez l'Eternel, car il est bon; parce que sa miséricorde demeure à toujours.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
2 Célébrez le Dieu des dieux; parce que sa miséricorde demeure à toujours.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
3 Célébrez le Seigneur des Seigneurs; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
4 Célébrez celui qui seul fait de grandes merveilles; parce que sa bonté demeure à toujours.
Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
5 Celui qui a fait avec intelligence les cieux; parce que sa bonté demeure à toujours;
Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
6 Celui qui a étendu la terre sur les eaux; parce que sa bonté demeure à toujours;
Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
7 Celui qui a fait les grands luminaires; parce que sa bonté demeure à toujours;
Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
8 Le soleil pour dominer sur le jour; parce que sa bonté demeure à toujours;
Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
9 La lune et les étoiles pour avoir domination sur la nuit; parce que sa bonté demeure à toujours;
Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
10 Celui qui a frappé l'Egypte en leurs premiers-nés; parce que sa bonté demeure à toujours;
Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
11 Et qui a fait sortir Israël du milieu d'eux; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
12 Et cela avec main forte et bras étendu; parce que sa bonté demeure à toujours.
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
13 Il a fendu la mer Rouge en deux; parce que sa bonté demeure à toujours;
Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
14 Et a fait passer Israël par le milieu d'elle; parce que sa bonté demeure à toujours:
Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
15 Et a renversé Pharaon et son armée dans la mer Rouge; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
16 Il a conduit son peuple par le désert; parce que sa bonté demeure à toujours.
Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
17 Il a frappé les grands Rois; parce que sa bonté demeure à toujours.
Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
18 Et a tué les Rois magnifiques; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
19 [Savoir], Sihon Roi des Amorrhéens; parce que sa bonté demeure à toujours;
Sihoni, ọba àwọn ará Amori
20 Et Hog Roi de Basan; parce que sa bonté demeure à toujours.
Àti Ogu, ọba Baṣani;
21 Et a donné leur pays en héritage; parce que sa bonté demeure à toujours;
Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
22 En héritage à Israël son serviteur; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
23 Et qui, lorsque nous étions fort abaissés, s'est souvenu de nous, parce que sa bonté demeure à toujours;
Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
24 Et nous a délivrés [de la main] de nos adversaires; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
25 Et il donne la nourriture à toute chair; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
26 Célébrez le Dieu des cieux; parce que sa bonté demeure à toujours.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;