< Psaumes 103 >
1 Psaume de David. Mon âme, bénis l'Eternel, et que tout ce qui est au-dedans de moi bénisse le Nom de sa Sainteté.
Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
2 Mon âme, bénis l'Eternel, et n'oublie pas un de ses bienfaits.
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
3 C'est lui qui te pardonne toutes tes iniquités, qui guérit toutes tes infirmités;
ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
4 Qui garantit ta vie de la fosse, qui te couronne de gratuité et de compassions;
ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
5 Qui rassasie ta bouche de biens; ta jeunesse est renouvelée comme celle de l'aigle.
ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
6 L'Eternel fait justice et droit à tous ceux à qui l'on fait tort.
Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
7 Il a fait connaître ses voies à Moïse, [et] ses exploits aux enfants d'Israël.
Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
8 L'Eternel est pitoyable, miséricordieux, tardif à colère, et abondant en grâce.
Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
9 Il ne dispute point éternellement, et il ne garde point à toujours [sa colère].
Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
10 Il ne nous a point fait selon nos péchés, et ne nous a point rendu selon nos iniquités.
Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
11 Car autant que les cieux sont élevés par-dessus la terre, autant sa gratuité est grande sur ceux qui le craignent.
Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
12 Il a éloigné de nous nos forfaits, autant que l'Orient est éloigné de l'Occident.
Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
13 De telle compassion qu'un père est ému envers ses enfants, de telle compassion l'Eternel est ému envers ceux qui le craignent.
Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
14 Car il sait bien de quoi nous sommes faits, se souvenant que nous ne sommes que poudre.
nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
15 Les jours de l'homme mortel sont comme le foin, il fleurit comme la fleur d'un champ.
Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
16 Car le vent étant passé par-dessus, elle n'est plus, et son lieu ne la reconnaît plus.
afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
17 Mais la miséricorde de l'Eternel est de tout temps, et elle sera à toujours en faveur de ceux qui le craignent; et sa justice en faveur des enfants de leurs enfants;
Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
18 Pour ceux qui gardent son alliance, et qui se souviennent de ses commandements pour les faire.
sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
19 L'Eternel a établi son Trône dans les cieux, et son règne a domination sur tout.
Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
20 Bénissez l'Eternel, vous ses Anges puissants en vertu, qui faites son commandement, en obéissant à la voix de sa parole.
Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
21 Bénissez l'Eternel, vous toutes ses armées, qui êtes ses Ministres faisant son bon plaisir.
Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
22 Bénissez l'Eternel, [vous] toutes ses œuvres, par tous les lieux de sa domination. Mon âme, bénis l'Eternel.
Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.