< Proverbes 30 >
1 Les paroles d'Agur fils de Jaké, [savoir] la charge que cet homme-là proféra à Ithiel, à Ithiel, [dis-je], et à Ucal.
Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
2 Certainement je suis le plus hébété de tous les hommes, et il n'y a point en moi de prudence humaine.
“Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
3 Et je n'ai point appris la sagesse; et saurais-je la science des saints?
Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
4 Qui est celui qui est monté aux cieux, et qui en est descendu? Qui est celui qui a renfermé le vent dans ses poings, qui a serré les eaux dans son manteau, qui a dressé toutes les bornes de la terre? Quel est son nom, et quel est le nom de son fils, si tu le connais?
Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
5 Toute la parole de Dieu est épurée; il est un bouclier à ceux qui ont leur refuge vers lui.
“Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
6 N'ajoute rien à ses paroles, de peur qu'il ne te reprenne, et que tu ne sois [trouvé] menteur.
Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
7 Je t'ai demandé deux choses, ne me les refuse point durant ma vie.
“Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
8 Eloigne de moi la vanité, et la parole de mensonge; ne me donne ni pauvreté ni richesses, nourris-moi du pain de mon ordinaire.
Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
9 De peur qu'étant rassasié je ne te renie, et que je ne dise: qui est l'Eternel? de peur aussi qu'étant appauvri, je ne dérobe, et que je ne prenne [en vain] le nom de mon Dieu.
Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
10 Ne blâme point le serviteur devant son maître, de peur que [ce serviteur] ne te maudisse, et qu'il ne t'en arrive du mal.
“Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
11 Il y a une race de gens qui maudit son père, et qui ne bénit point sa mère.
“Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
12 Il y a une race de gens qui pense être nette, et qui toutefois n'est point lavée de son ordure.
Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
13 Il y a une race de gens de laquelle les yeux sont fort hautains, et dont les paupières sont élevées.
àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
14 Il y a une race de gens dont les dents sont des épées, et dont les dents mâchelières sont des couteaux, pour consumer de dessus la terre les affligés et les nécessiteux d'entre les hommes.
Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
15 La sangsue a deux filles, [qui disent]: Apporte, apporte. Il y a trois choses qui ne se rassasient point; il y en a même quatre qui ne disent point; C'est assez:
“Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
16 Le sépulcre, la matrice stérile, la terre qui n'est point rassasiée d'eau, et le feu qui ne dit point: C'est assez. (Sheol )
Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol )
17 L'œil [de celui] qui se moque de son père, et qui méprise l'enseignement de sa mère, les corbeaux des torrents le crèveront, et les petits de l'aigle le mangeront.
“Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
18 Il y a trois choses qui sont trop merveilleuses pour moi, même quatre, [lesquelles] je ne connais point;
“Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
19 Savoir, la trace de l'aigle dans l'air, la trace du serpent sur un rocher, le chemin d'un navire au milieu de la mer, et la trace de l'homme vers la vierge.
ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
20 Telle est la trace de la [femme] adultère; elle mange, et s'essuie la bouche, puis elle dit: Je n'ai point commis d'iniquité.
“Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
21 La terre tremble pour trois choses, même pour quatre, lesquelles elle ne peut porter:
“Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
22 Pour le serviteur quand il règne; pour l'insensé quand il est rassasié de viande;
Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
23 Pour la [femme] digne d'être haïe, quand elle se marie; et pour la servante quand elle hérite de sa maîtresse.
obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
24 Il y a quatre choses très-petites en la terre qui toutefois sont bien sages et bien avisées:
“Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
25 Les fourmis, qui sont un peuple faible, et qui néanmoins préparent durant l'été leur nourriture.
Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
26 Les lapins, qui sont un peuple sans force, et qui néanmoins font leurs maisons dans les rochers;
Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
27 Les sauterelles, qui n'ont point de Roi, et qui toutefois vont toutes par bandes.
àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
28 L'araignée, qui saisit [les mouches] avec ses pieds, et qui est pourtant dans les palais des Rois.
Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
29 Il y a trois choses qui ont un beau marcher, même quatre, qui ont une belle démarche:
“Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
30 Le lion, qui est le plus fort d'entre les bêtes, et qui ne tourne point en arrière pour la rencontre de qui que ce soit;
Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
31 [Le cheval], qui a les flancs bien troussés; le bouc; et le Roi, devant qui personne ne peut subsister.
Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
32 Si tu t'es porté follement en t'élevant, et si tu as mal pensé, mets ta main sur la bouche.
“Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
33 Comme celui qui bat le lait, en fait sortir le beurre; et celui qui presse le nez, en fait sortir le sang; ainsi celui qui presse la colère, excite la querelle.
Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”