< Proverbes 20 >
1 Le vin est moqueur, et la cervoise est mutine; et quiconque y excède, n'est pas sage.
Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
2 La terreur du Roi est comme le rugissement d'un jeune lion; celui qui se met en colère contre lui, pèche contre soi-même.
Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
3 C'est une gloire à l'homme de s'abstenir de procès; mais chaque insensé s'en mêle.
Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
4 Le paresseux ne labourera point à cause du mauvais temps, mais il mendiera durant la moisson, et il n'aura rien.
Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
5 Le conseil dans le cœur d'un [digne] personnage est [comme] des eaux profondes, et l'homme intelligent l'y puisera.
Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
6 La plupart des hommes prêchent leur bonté; mais qui est-ce qui trouvera un homme véritable?
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
7 Ô! que les enfants du juste qui marchent dans son intégrité, seront heureux après lui!
Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8 Le Roi séant sur le trône de justice dissipe tout mal par son regard.
Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9 Qui est-ce qui peut dire: J'ai purifié mon cœur; je suis net de mon péché?
Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10 Le double poids et la double mesure sont tous deux en abomination à l'Eternel.
Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
11 Un jeune enfant même fait connaître par ses actions si son œuvre sera pure, et si elle sera droite.
Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12 Et l'oreille qui entend, et l'œil qui voit, l'Eternel les a faits tous les deux.
Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13 N'aime point le sommeil, de peur que tu ne deviennes pauvre; ouvre tes yeux, et tu auras suffisamment de pain.
Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
14 Il est mauvais, il est mauvais, dit l'acheteur; puis il s'en va, et se vante.
“Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
15 Il y a de l'or, et beaucoup de perles; mais les lèvres qui prononcent la science sont un vase précieux.
Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16 Quand quelqu'un aura cautionné pour l'étranger, prends son vêtement, et prends gage de lui pour l'étrangère.
Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17 Le pain volé est doux à l'homme; mais ensuite sa bouche sera remplie de gravier.
Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
18 Chaque pensée s'affermit par le conseil; fais donc la guerre avec prudence.
Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
19 Celui qui révèle le secret va médisant; ne te mêle donc point avec celui qui séduit par ses lèvres.
Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
20 La lampe de celui qui maudit son père, ou sa mère, sera éteinte dans les ténèbres les plus noires.
Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21 L'héritage pour lequel on s'est trop hâté du commencement, ne sera point béni sur la fin.
Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22 Ne dis point: je rendrai le mal; mais attends l'Eternel, et il te délivrera.
Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23 Le double poids est en abomination à l'Eternel, et la fausse balance n'[est] pas bonne.
Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24 Les pas de l'homme sont de par l'Eternel, comment donc l'homme entendra-t-il sa voie?
Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
25 C'est un piège à l'homme d'engloutir la chose sainte, et de chercher à s'emparer des choses vouées.
Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
26 Le sage Roi dissipe les méchants, et fait tourner la roue sur eux.
Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
27 C'est une lampe de l'Eternel que l'esprit de l'homme; elle sonde jusqu'aux choses les plus profondes.
Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
28 La bonté et la vérité conserveront le Roi; et il soutient son trône par ses faveurs.
Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
29 La force des jeunes gens est leur gloire; et les cheveux blancs sont l'honneur des anciens.
Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
30 La meurtrissure de la plaie est un nettoiement au méchant, et des coups qui pénètrent jusqu'au fond de l'âme.
Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.