< Nahum 3 >
1 Malheur à la ville sanguinaire qui est toute pleine de mensonge, et toute remplie de proie; la rapine ne s'en retirera point:
Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì, gbogbo rẹ̀ kún fún èké, ó kún fún olè, ìjẹ kò kúrò!
2 Ni le bruit du fouet, ni le bruit impétueux des roues, ni les chevaux battant des pieds, ni les chariots sautelant.
Ariwo pàṣán àti ariwo kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun àti jíjó ẹṣin àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
3 Ni les gens de cheval faisant bondir [leurs chevaux], ni l'épée brillante, ni la hallebarde étincelante, ni la multitude des blessés à mort, ni le grand nombre des corps morts, et il n'y aura nulle fin aux corps morts, de sorte qu'on sera renversé sur leurs corps.
Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè! Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú; òkú kò sì ni òpin; àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
4 A cause de la multitude des prostitutions de cette prostituée pleine de charmes, experte en sortilèges, qui vendait les nations par ses prostitutions, et les familles par ses enchantements.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà àgbèrè tí ó rójú rere gbà, ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn Orílẹ̀-èdè di ẹrú nípa àgbèrè rẹ̀ àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.
5 Voici, j'en veux à toi, dit l'Eternel des armées, je te dépouillerai de tes vêtements; je manifesterai ta honte aux nations, et ton ignominie aux Royaumes.
“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ. Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
6 Je ferai tomber sur ta tête la peine de tes abominations, je te consumerai et je te couvrirai d'infamie.
Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara, èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
7 Et il arrivera que quiconque te verra s'éloignera de toi, et dira: Ninive est détruite; qui aura compassion d'elle? D'où te chercherai-je des consolateurs?
Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé, ‘Ninefe ṣòfò, ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’ Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”
8 Vaux-tu mieux que No la nourricière, située entre les fleuves, qui a les eaux à l'entour de soi, dont la mer est le rempart, à qui la mer sert de murailles?
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ, èyí tí ó wà ní ibi odò Naili, tí omi sì yí káàkiri? Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀, omi si jẹ́ odi rẹ̀.
9 Sa force était Cus et l'Egypte, et une infinité d'autres [peuples]; Put et les Lybiens sont allés à son secours.
Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin; Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
10 Elle-même aussi a été transportée [hors de sa terre], elle s'en est allée en captivité; même ses enfants ont été écrasés aux carrefours de toutes les rues, et on a jeté le sort sur ses gens honorables, et tous ses Principaux ont été liés de chaînes.
Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn o sì lọ sí oko ẹrú. Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀ ní orí ìta gbogbo ìgboro. Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin, gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè.
11 Toi aussi tu seras enivrée, tu te tiendras cachée, et tu chercheras du secours contre l'ennemi.
Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara; a ó sì fi ọ́ pamọ́ ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.
12 Toutes tes forteresses seront [comme] des figues, et comme des premiers fruits, qui étant secoués, tombent dans la bouche de celui qui les veut manger.
Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn; nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n, ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
13 Voici, ton peuple sera comme autant de femmes au milieu de toi; les portes de ton pays seront toutes ouvertes à tes ennemis; le feu consumera tes barres.
Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun! Obìnrin ni gbogbo wọn. Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada, fún àwọn ọ̀tá rẹ; iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.
14 Puise-toi de l'eau pour le siége, fortifie tes remparts, enfonce [le pied] dans la terre grasse, et foule l'argile, et rebâtis la briqueterie.
Pọn omi nítorí ìhámọ́, mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i wọ inú amọ̀ kí o sì tẹ erùpẹ̀, kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
15 Là le feu te consumera; l'épée te retranchera, elle te dévorera comme le hurebec [dévore les arbres]. Qu'on s'amasse comme les hurebecs, amasse-toi comme les sauterelles.
Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run; idà yóò sì ké ọ kúrò, yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò, yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata, àní, di púpọ̀ bí eṣú!
16 Tu as multiplié tes négociants en plus grand nombre que les étoiles des cieux; les hurebecs s'étant répandus ont tout ravagé, et puis ils s'en sont envolés.
Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀ títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ, ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
17 Ceux qui portent le diadème au milieu de toi sont comme des sauterelles, et tes capitaines comme de grandes sauterelles qui se campent dans les cloisons au temps de la fraîcheur, et qui, lorsque le soleil est levé, s'écartent, de sorte qu'on ne connaît plus le lieu où elles ont été.
Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú, àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá, èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù, ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ, ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.
18 Tes Pasteurs se sont endormis, ô Roi d'Assyrie! tes hommes illustres se sont tenus dans leurs tentes; ton peuple est dispersé par les montagnes, et il n'[y a] personne qui le rassemble.
Ìwọ ọba Asiria, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé; àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi. Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá, tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
19 Il n'y a point de remède à ta blessure, ta plaie est douloureuse; tous ceux qui entendront parler de toi battront des mains sur toi; car qui est-ce qui n'a pas continuellement éprouvé les effets de ta malice?
Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn; ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora, Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí, nítorí ta ni kò ní pín nínú ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.