< Michée 3 >

1 C'est pourquoi j'ai dit: Ecoutez maintenant, Chefs de Jacob, et vous Conducteurs de la maison d'Israël: N'est ce point à vous de connaître ce qui est juste?
Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
2 Ils haïssent le bien, et aiment le mal; ils ravissent la peau de ces gens-ci de dessus eux, et leur chair de dessus leurs os.
Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
3 Et ce qu'ils mangent; c'est la chair de mon peuple, et ils ont écorché leur peau de dessus eux, et ont cassé leurs os, et les ont mis par pièces comme dans un pot, et comme de la chair dans une chaudière.
àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
4 Alors ils crieront à l'Eternel, mais il ne les exaucera point, et il cachera sa face d'eux en ce temps-là, selon qu'ils se sont mal conduits dans leurs actions.
Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
5 Ainsi a dit l'Eternel contre les Prophètes qui font égarer mon peuple, qui mordent de leurs dents, et qui crient: Paix! et si quelqu'un ne leur donne rien dans leur bouche, ils publient la guerre contre lui.
Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
6 C'est pourquoi la nuit sera sur vous, afin que vous n'ayez point de vision; et elle s'obscurcira, afin que vous ne deviniez point; le soleil se couchera sur ces Prophètes-là, et le jour leur sera ténébreux.
Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
7 Et [les] voyants seront honteux, et les devins rougiront de honte; eux tous se couvriront sur la lèvre de dessus, parce qu'il n'y aura aucune réponse de Dieu.
Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
8 Mais moi, je suis rempli de force, et de jugement, et de courage, par l'Esprit de l'Eternel, pour déclarer à Jacob son crime, et à Israël son péché.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
9 Ecoutez maintenant ceci, Chefs de la maison de Jacob, et vous Conducteurs de la maison d'Israël, qui avez le jugement en abomination, et qui pervertissez tout ce qui est juste.
Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
10 On bâtit Sion de sang, et Jérusalem d'injustices.
tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
11 Ses Chefs jugent pour des présents, ses Sacrificateurs enseignent pour le salaire, et ses prophètes devinent pour de l'argent, puis ils s'appuient sur l'Eternel, en disant: L'Eternel n'est-il pas parmi nous? Il ne viendra point de mal sur nous.
Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
12 C'est pourquoi à cause de vous, Sion sera labourée [comme] un champ, et Jérusalem sera réduite en monceaux [de pierres], et la montagne du Temple en hauts lieux de forêt.
Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

< Michée 3 >