< Jérémie 7 >
1 La parole fut [adressée] à Jérémie par l'Eternel, en disant:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 Tiens-toi debout à la porte de la maison de l'Eternel, et y crie cette parole, et dis: vous tous hommes de Juda qui entrez par ces portes, pour vous prosterner devant l'Eternel, écoutez la parole de l'Eternel;
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: corrigez votre vie et vos actions, et je vous ferai habiter en ce lieu-ci.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Ne vous fiez point sur des paroles trompeuses, en disant: c'est ici le Temple de l'Eternel, le Temple de l'Eternel, le Temple de l'Eternel.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Mais corrigez sérieusement votre conduite et vos actions, et appliquez-vous à faire droit à ceux qui plaident l'un contre l'autre.
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 Et ne faites point de tort à l'étranger, ni à l'orphelin, ni à la veuve; et ne répandez point en ce lieu-ci le sang innocent, et ne marchez point après les dieux étrangers, à votre ruine.
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 Et je vous ferai habiter depuis un siècle jusqu’à l'autre siècle en ce lieu-ci, au pays que j'ai donné à vos pères.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Voici, vous vous fiez sur des paroles trompeuses, sans aucun profit.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Ne dérobez-vous pas? ne tuez-vous pas? ne commettez-vous pas adultère? ne jurez-vous pas faussement? ne faites-vous pas des encensements à Bahal? n'allez-vous pas après les dieux étrangers, que vous ne connaissez point?
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 Toutefois vous venez, et vous vous présentez devant moi dans cette maison, sur laquelle mon Nom est réclamé, et vous dites: nous avons été délivrés pour faire toutes ces abominations.
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Cette maison, sur laquelle mon Nom est réclamé devant vos yeux, n'est-elle pas devenue une caverne de brigands? et voici, moi-même je l'ai vu, dit l'Eternel.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Mais allez maintenant à mon lieu, qui était à Silo, là où j'avais placé mon Nom dès le commencement, et regardez ce que je lui ai fait, à cause de la malice de mon peuple d'Israël.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Maintenant donc, parce que vous faites toutes ces choses, dit l'Eternel, et que je vous ai parlé, me levant dès le matin, et parlant, et que vous n'avez point écouté; je vous ai appelés, et vous n'avez point répondu:
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Je ferai à cette maison, sur laquelle mon Nom est réclamé, et sur laquelle vous vous fiez, et à ce lieu que je vous ai donné à vous et à vos pères, comme j'ai fait à Silo.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Et je vous chasserai de devant ma face, comme j'ai chassé tous vos frères, avec toute la postérité d'Ephraïm.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Toi donc ne prie point pour ce peuple, et ne jette point de cri, et ne fais point de requête pour eux, et n'intercède point envers moi; car je ne t'exaucerai point.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Ne vois-tu pas ce qu'ils font dans les villes de Juda, et dans les rues de Jérusalem?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Les fils amassent le bois, et les pères allument le feu, et les femmes pétrissent la pâte pour faire des gâteaux à la Reine des cieux; et pour faire des aspersions aux dieux étrangers, afin de m'irriter.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Ce qu'ils m'irritent est-il contre moi? dit l'Eternel. N'est-ce pas contre eux-mêmes, à la confusion de leurs faces?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 C'est pourquoi ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: voici, ma colère et ma fureur vont fondre sur ce lieu-ci, sur les hommes et sur les bêtes, sur les arbres des champs, et sur le fruit de la terre, ma colère s'embrasera, et ne s'éteindra point.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: ajoutez vos holocaustes à vos sacrifices, et mangez-en la chair.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Car je n'ai point parlé avec vos pères, et je ne leur ai point donné de commandement touchant les holocaustes et les sacrifices, au jour que je les fis sortir du pays d'Egypte.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Mais voici ce que je leur ai commandé, disant: écoutez ma voix, et je serai votre Dieu, et vous serez mon peuple; et marchez dans toutes les voies que je vous ai ordonnées, afin que vous soyez heureux.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Mais ils n'ont point écouté, et n'ont point incliné leur oreille; mais ils ont suivi [d'autres] conseils, et la dureté de leur cœur mauvais, ils se sont éloignés et ne sont point retournés jusques à moi.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Depuis le jour que vos pères sont sortis du pays d'Egypte, jusqu’à aujourd'hui, je vous ai envoyé tous mes serviteurs Prophètes, me levant [chaque] jour dès le matin, et les envoyant.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Mais ils ne m'ont point écouté, et ils n'ont point incliné leur oreille, mais ils ont raidi leur cou; ils ont fait pis que leurs pères.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Tu leur diras donc toutes ces paroles, mais ils ne t'écouteront point; et tu crieras après eux, mais ils ne te répondront point.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 C'est pourquoi tu leur diras: [c'est] ici la nation qui n'a point écouté la voix de l'Eternel son Dieu, et qui n'a point reçu d'instruction; la fidélité est périe, et elle a été retranchée de leur bouche.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Tonds ta chevelure, [ô Jérusalem!] et [la] jette au loin, et prononce à haute voix ta complainte sur les lieux élevés; car l'Eternel a rejeté et abandonné la génération contre laquelle il est fort courroucé.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Parce que les enfants de Juda ont fait ce qui me déplaît, dit l'Eternel, ils ont mis leurs abominations dans cette maison, sur laquelle mon Nom est invoqué, afin de la souiller.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Et ils ont bâti les hauts lieux de Topheth, qui [est] dans la vallée du fils de Hinnom, pour brûler leurs fils et leurs filles au feu, ce que je n'ai pas commandé, et à quoi je n'ai jamais pensé.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 C'est pourquoi voici, les jours viennent, dit l'Eternel, qu'elle ne sera plus appelée Topheth, ni la vallée du fils de Hinnom, mais la vallée de la tuerie, et on ensevelira [les morts] à Topheth, à cause qu'il n'y aura plus [d'autre] lieu.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 Et les corps morts de ce peuple seront pour viande aux oiseaux des cieux, et aux bêtes de la terre, sans qu'il y ait personne qui les effarouche.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Je ferai aussi cesser des villes de Juda, et des rues de Jérusalem, la voix de joie, et la voix d'allégresse, la voix de l'époux, et la voix de l'épouse, car le pays sera mis en désolation.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.