< Isaïe 56 >
1 Ainsi a dit l'Eternel; observez la justice, et faites ce qui est juste; car mon salut est prêt à venir; et ma justice à être révélée.
Èyí ni ohun ti Olúwa sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
2 O que bienheureux est l'homme qui fera cela, et le fils de l'homme [qui] s'y tiendra, observant le Sabbat de peur de le profaner, et gardant ses mains de faire aucun mal.
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”
3 Et que l'enfant de l'étranger qui se sera joint à l'Eternel, ne parle point, en disant; l'Eternel me sépare entièrement de son peuple; et que l'eunuque ne dise point; voici, je suis un arbre sec.
Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ Olúwa sọ wí pé, “Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé, “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”
4 Car ainsi a dit l'Eternel touchant les eunuques; ceux qui garderont mes Sabbats, et qui choisiront ce en quoi je prends plaisir, et se tiendront à mon alliance;
Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
5 Je leur donnerai dans ma maison et dans mes murailles une place et un nom meilleur que le nom de fils ou de filles; je leur donnerai à chacun une réputation perpétuelle, qui ne sera point retranché.
fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin, Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.
6 Et quant aux enfants de l'étranger qui se seront joints à l'Eternel, pour le servir, et pour aimer le Nom de l'Eternel, afin de lui être serviteurs, [savoir] tous ceux qui gardent le sabbat de peur de le profaner, et qui se tiennent à mon alliance;
Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ Olúwa àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
7 Je les amènerai aussi à la montagne de ma sainteté, et je les réjouirai dans la maison dans laquelle on m'invoque, leurs holocaustes et leurs sacrifices seront agréables sur mon autel; car ma maison sera appelée, la maison de prière pour tous les peuples.
àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi, èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn, ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
8 Encore en assemblerai-je vers lui outre ceux qui y sont assemblés, dit le Seigneur l'Eternel, qui rassemble les exilés d'Israël.
Olúwa Olódùmarè sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”
9 Bêtes des champs, bêtes des forêts, venez toutes pour manger.
Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
10 Toutes ses sentinelles sont aveugles; elles ne savent rien; ce sont tous des chiens muets qui ne peuvent aboyer, dormant et demeurant couchés, et aimant à sommeiller.
Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
11 Ce sont des chiens goulus, qui ne savent ce que c'est que d'être rassasiés; et ce sont des pasteurs qui ne savent rien comprendre; ils se sont tous tournés à leur train, chacun à son gain déshonnête dans son quartier, [en disant]:
Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
12 Venez, je prendrai du vin et nous nous enivrerons de cervoise; et le jour de demain sera comme celui d'aujourd'hui, même beaucoup plus grand.
Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, “Wá, fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”