< Isaïe 16 >
1 Envoyez l'agneau au Dominateur de la terre, envoyez-le du rocher du désert, à la montagne de la fille de Sion.
Fi ọ̀dọ́-àgùntàn ṣe ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí aláṣẹ ilẹ̀ náà, láti Sela, kọjá ní aginjù, lọ sí orí òkè ọ̀dọ́mọbìnrin Sioni.
2 Car il arrivera que les filles de Moab seront au passage d'Arnon, comme un oiseau volant çà et là, [comme] une nichée chassée de son nid.
Gẹ́gẹ́ bí alárìnkiri ẹyẹ tí a tì jáde kúrò nínú ìtẹ́, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn obìnrin Moabu ní àwọn ìwọdò Arnoni.
3 Mets en avant le conseil, fais l'ordonnance, sers d'ombre comme une nuit au milieu du midi; cache ceux qui ont été chassés, et ne décèle point ceux qui sont errants.
“Fún wa ní ìmọ̀ràn ṣe ìpinnu fún wa. Jẹ́ kí òjìji rẹ dàbí òru, ní ọ̀sán gangan. Fi àwọn ìsáǹsá pamọ́, má ṣe fi àwọn aṣàtìpó han.
4 Que ceux de mon peuple qui ont été chassés séjournent chez toi, ô Moab! sois leur une retraite contre celui qui fait le dégât; car celui qui usait d'extorsion a cessé, le dégât a pris fin, ceux qui foulaient sont consumés de dessus la terre.
Jẹ́ kí àwọn ìsáǹsá Moabu gbé pẹ̀lú rẹ, jẹ́ ààbò fún wọn kúrò lọ́wọ́ ìparun.” Aninilára yóò wá sí òpin, ìparun yóò dáwọ́ dúró; òfinràn yóò pòórá kúrò lórí ilẹ̀.
5 Et le trône sera établi par la gratuité; et sur ce trône sera assis en vérité, dans le tabernacle de David, un qui jugera, qui recherchera le droit, et qui se hâtera de faire justice.
Nínú ìfẹ́ a ó fi ìdí ìjọba kan múlẹ̀, ní òdodo ọkùnrin kan yóò jókòó lórí rẹ̀ ẹnìkan láti ilé Dafidi wá. Ẹni yóò ṣe ìdájọ́, yóò sì máa wá ìdájọ́, yóò sì máa yára wá ohun tí í ṣe òdodo.
6 Nous avons entendu l'orgueil de Moab le très-orgueilleux, sa fierté, et son orgueil, et son arrogance; ceux sur qui il s'appuie ne sont rien de ferme.
Àwa ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu, ìwọ̀sí ìgbéraga rẹ̀ àti fùlenge fùlenge, gààrù rẹ̀ àti àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n ìfọ́nnu rẹ̀ jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.
7 C'est pourquoi Moab hurlera sur Moab, chacun hurlera; vous grommellerez pour les fondements de Kir-Haréseth; il n'y aura que des gens blessés à mort.
Nítorí náà ni àwọn ará Moabu hu, wọ́n jùmọ̀ hu lórí Moabu. Sọkún kí o sì banújẹ́ fún àkàrà díndín Kiri-Hareseti.
8 Car les guérets de Hesbon, et le vignoble de Sibma, languissent; les Seigneurs des nations ont foulé ses meilleurs plants, [qui] atteignaient jusques à Jahzer, ils couraient çà et là par le désert, et ses provins s'étendaient et passaient au delà de la mer.
Gbogbo pápá oko Heṣboni ti gbẹ, bákan náà ni àjàrà Sibma rí. Àwọn aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n tẹ àwọn àyànfẹ́ àjàrà mọ́lẹ̀, èyí tí ó ti fà dé Jaseri ó sì ti tàn dé agbègbè aginjù. Àwọn èhíhù rẹ̀ fọ́n jáde, ó sì lọ títí ó fi dé Òkun.
9 C'est pourquoi je pleurerai du pleur de Jahzer, le vignoble de Sibma; je t'arroserai de mes larmes, ô Hesbon et Elhalé! car l'ennemi avec des cris s'est jeté sur tes fruits d'Eté, et sur ta moisson.
Nítorí náà mo sọkún, gẹ́gẹ́ bí Jaseri ṣe sọkún, fún àwọn àjàrà Sibma. Ìwọ Heṣboni, ìwọ Eleale, mo bomirin ọ́ pẹ̀lú omi ojú! Igbe ayọ̀ lórí àwọn èso pípọ́n rẹ àti lórí ìkórè èyí tí o ti mọ́wọ́ dúró.
10 Et la joie et la gaieté s'est retirée du champ fertile; on ne se réjouira plus, et on ne s'égayera plus dans les vignes, celui qui foulait le vin ne le foulera plus dans les cuves, j'ai fait cesser la chanson de la vendange.
Ayọ̀ àti ìdùnnú ni a ti mú kúrò nínú ọgbà-igi eléso rẹ; kò sí ẹnìkan tí ó kọrin tàbí kígbe nínú ọgbà àjàrà: ẹnikẹ́ni kò fún ọtí níbi ìfúntí, nítorí mo ti fi òpin sí gbogbo igbe.
11 C'est pourquoi mes entrailles mèneront du bruit comme une harpe sur Moab, et mon ventre sur Kir-Hérès.
Ọkàn mi kérora fún Moabu gẹ́gẹ́ bí i dùùrù, àní tọkàntọkàn mi fún ìlú Kiri-Hareseti.
12 Et il arrivera qu'on verra que Moab se lassera [pour aller] au haut lieu, et qu'il entrera en son saint lieu pour prier; mais il ne pourra rien obtenir.
Nígbà tí Moabu farahàn ní ibi gíga rẹ̀, ó ṣe ara rẹ̀ ní wàhálà lásán; nígbà tí ó lọ sí ojúbọ rẹ̀ láti gbàdúrà òfo ni ó jásí.
13 C'est là la parole que l'Eternel a prononcée depuis longtemps sur Moab.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa Moabu.
14 Et maintenant l'Eternel a parlé, en disant; dans trois ans, tels que sont les ans d'un mercenaire, la gloire de Moab sera avilie, avec toute cette grande multitude; et le résidu sera petit, ce sera peu de chose, ce ne sera rien de considérable.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí Olúwa wí pé, “Láàrín ọdún mẹ́ta gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ìdè ọgbà rẹ̀ ti máa kà á, ògo Moabu àti àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn rẹ̀ ni a ó kẹ́gàn, àwọn tí ó sálà nínú rẹ̀ yóò kéré níye, wọn yóò sì jẹ́ akúrẹtẹ̀.”