< Ézéchiel 35 >

1 La parole de l'Eternel me fut encore [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Fils d'homme, tourne ta face contre la montagne de Séhir, et prophétise contre elle.
“Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
3 Et lui dis: ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: voici, j'en veux à toi, montagne de Séhir, et j'étendrai ma main contre toi, et te réduirai en désolation et en désert.
kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
4 Je réduirai tes villes en désert, et tu [ne] seras [que] désolation, et tu connaîtras que je suis l'Eternel.
Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
5 Parce que tu as eu une inimitié immortelle, et que tu as fait couler le sang des enfants d'Israël à coups d'épée, au temps de leur calamité, et au temps de leur iniquité, [qui en a été] la fin.
“‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
6 C'est pourquoi je suis vivant, dit le Seigneur l'Eternel, que je te mettrai toute en sang, et le sang te poursuivra; parce que tu n'as point haï le sang, le sang aussi te poursuivra.
nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
7 Et je réduirai la montagne de Séhir en désolation et en désert, et j'en éloignerai tous ceux qui la fréquentaient.
Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
8 Et je remplirai ses montagnes de ses gens mis à mort; tes hommes tués par l'épée tomberont en tes coteaux, et en tes vallées, et en tous tes courants d'eaux.
Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
9 Je te réduirai en désolations éternelles, et tes villes ne seront plus habitées; et vous saurez que je suis l'Eternel.
Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
10 Parce que tu as dit: les deux nations, et les deux pays seront à moi, et nous les posséderons, quoique l'Eternel ait été là.
“‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
11 A cause de cela, je suis vivant, dit le Seigneur l'Eternel, que j'agirai selon ton courroux, et selon ton envie que tu as exécutée, à cause de tes haines contre eux; et je serai connu entre eux quand je t'aurai jugé.
nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
12 Et tu sauras que moi l'Eternel j'ai ouï toutes les paroles insultantes que tu as prononcées contre les montagnes d'Israël, en disant: elles ont été désolées, elles nous ont été données pour les consumer.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
13 Et vous m'avez bravé par vos discours, et vous avez multiplié vos paroles contre moi; je l'ai ouï.
Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
14 Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: quand toute la terre se réjouira, je te réduirai en désolation.
Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
15 Comme tu t'es réjouie sur l'héritage de la maison d'Israël, parce qu'il a été désolé, j'en ferai de même envers toi; tu ne seras que désolation, ô montagne de Séhir! même tout Edom entièrement; et ils sauront que je suis l'Eternel.
Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ézéchiel 35 >