< Ézéchiel 23 >

1 La parole de l'Eternel me fut encore [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Fils d'homme, il y a eu deux femmes, filles d'une même mère,
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Qui se sont prostituées en Egypte, elles se sont abandonnées dans leur jeunesse: là leur sein fut déshonoré et leur virginité flétrie.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Et c'étaient ici leurs noms, celui de la plus grande était Ahola, et celui de sa sœur, Aholiba; elles étaient à moi, et elles ont enfanté des fils et des filles; leurs noms donc étaient Ahola, qui était Samarie; et Aholiba, qui est Jérusalem.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Or Ahola a commis adultère étant ma femme, et s'est rendue amoureuse de ses amoureux, [c'est-à-dire], des Assyriens ses voisins;
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 Vêtus de pourpre, gouverneurs, et magistrats, tous jeunes et aimables, tous cavaliers, montés sur des chevaux.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 Et elle a commis ses adultères avec eux, qui tous étaient l'élite des enfants des Assyriens, et avec tous ceux de qui elle s'est rendue amoureuse, et s'est souillée avec toutes leurs idoles.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 Elle n'a pas même quitté ses fornications [qu'elle avait apportées] d'Egypte, où l'on avait couché avec elle dans sa jeunesse, où l'on avait déshonoré sa virginité et où ils s'étaient livrés à l'impureté avec elle.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 C'est pourquoi je l'ai livrée entre les mains de ses amoureux, entre les mains, [dis-je], des enfants des Assyriens, dont elle s'était rendue amoureuse.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 Ils l'ont couverte d'opprobre, ils ont enlevé ses fils et ses filles, et l'ont tuée elle-même avec l'épée, et elle a été fameuse entre les femmes, après qu'ils ont exercé des jugements sur elle.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 Et quand sa sœur Aholiba a vu cela, elle a fait pis qu'elle dans ses amours; même elle a fait pis dans ses débauches, que sa sœur n'avait fait dans les siennes.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Elle s'est rendue amoureuse des enfants des Assyriens, des gouverneurs et des magistrats ses voisins, vêtus magnifiquement, et des cavaliers montés sur des chevaux, tous jeunes et bien faits.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 Et j'ai vu qu'elle s'était souillée, et que c'était un même train de toutes les deux.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Et encore a-t-elle augmenté ses impudicités, car ayant vu des hommes portraits sur la paroi, les images des Caldéens, peints de vermillon;
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 Ceints de baudriers sur leurs reins, et ayant des habillements de tête flottants et teints, eux tous ayant l'apparence de grands Seigneurs, et la ressemblance des enfants de Babylone en Caldée; terre de leur naissance.
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 Elle s'en est rendue amoureuse par le regard de ses yeux, et a envoyé des messagers vers eux au pays des Caldéens.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Et les enfants de Babylone sont venus vers elle au lit de ses prostitutions, et l'ont souillée par leurs adultères; et elle s'est aussi souillée avec eux; et après cela son cœur s'est détaché d'eux.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Elle a donc manifesté ses fornications et fait connaître son opprobre; et mon cœur s'est détaché d'elle, comme mon cœur s'était détaché de sa sœur.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Car elle a multiplié ses adultères, jusqu'à rappeler le souvenir des jours de sa jeunesse, auxquels elle s'était abandonnée au pays d'Egypte.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 Et s'est rendue amoureuse de leurs fornicateurs, la chair desquels est [comme] la chair des ânes; et dont la force égale celle des chevaux.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Tu as donc repris les actions de ta jeunesse, lorsque tu as été déshonorée, depuis que tu étais en Egypte, à cause du sein de ta jeunesse.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 C'est pourquoi, ô Aholiba, ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: voici, je m'en vais réveiller contre toi tous tes amoureux, desquels ton cœur s'est détaché, et je les amènerai contre toi tout à l'environ.
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 [Savoir] les enfants de Babylone, et tous les Caldéens, Pekod, Soah, Koah, et tous les Assyriens avec eux, tous jeunes gens d'élite, gouverneurs et magistrats, grands Seigneurs, et renommés, tous montant à cheval.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 Et ils viendront contre toi avec des chars, des chariots, et des charrettes, et avec un grand amas de peuples; et ils emploieront contre toi de toutes parts, des écus, des boucliers, et des casques, et je leur mettrai le jugement en main, et ils te jugeront selon leur jugement.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 Et je mettrai ma jalousie contre toi, et ils agiront contre toi avec fureur; ils te retrancheront le nez et les oreilles; et ce qui sera demeuré de reste en toi tombera par l'épée. Ils enlèveront tes fils et tes filles; et ce qui sera demeuré de reste en toi sera dévoré par le feu.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 Ils te dépouilleront de tes vêtements, et enlèveront les ornements dont tu te pares.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Et je ferai cesser en toi ton énormité, et ta fornication [que tu as apportée] du pays d'Egypte, et tu ne lèveras plus tes yeux vers eux, et ne te souviendras plus de l'Egypte.
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 Car ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: voici, je vais te livrer en la main de ceux que tu hais, en la main de ceux de qui ton cœur s'est détaché.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 Ils te traiteront avec haine, et enlèveront tout ton travail, et te laisseront sans habits et découverte, et la turpitude de tes adultères, et de ton énormité, et de tes fornications, sera découverte.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 On te fera ces choses-là parce que tu t'es prostituée aux nations, avec lesquelles tu t'es souillée par leurs idoles.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Tu as marché dans le chemin de ta sœur, c'est pourquoi je mettrai sa coupe en ta main.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: tu boiras la coupe profonde et large de ta sœur qui sera une coupe d'une grande mesure; tu seras en dérision et en moquerie.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Tu seras remplie d'ivresse et de douleur, par la coupe de désolation et de dégât, qui est la coupe de ta sœur Samarie.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Tu la boiras, et la suceras, et tu briseras ses vaisseaux de terre et tu déchireras ton sein: car j'ai parlé, dit le Seigneur l'Eternel.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 C'est pourquoi ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: parce que tu m'as mis en oubli, et que tu m'as jeté derrière ton dos, aussi porteras-tu la peine de ton énormité, et de tes adultères.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 Puis l'Eternel me dit: fils d'homme, ne jugeras-tu pas Ahola et Aholiba? déclare-leur donc leurs abominations.
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 [Déclare-leur] comment elles ont commis adultère et comment il y a du sang dans leurs mains; comment, dis-je, elles ont commis adultère avec leurs idoles, et ont même fait passer [par le feu] leurs enfants pour les consumer, ces enfants qu'elles m'avaient enfantés.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Voici encore ce qu'elles m'ont fait; elles ont souillé mon saint lieu ce même jour-là, et ont profané mes Sabbats.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 Car après avoir égorgé leurs enfants à leurs idoles, elles sont entrées ce même jour-là dans mon saint lieu pour le profaner; et voilà, comment elles ont fait au milieu de ma maison.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 Et qui plus est, elles ont envoyé vers des hommes d'un pays éloigné, qui sont venus aussitôt que les messagers leur ont été envoyés; [et] pour l'amour d'eux tu t'es lavée, et tu as fardé ton visage, et t'es parée d'ornement.
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 Et t'es assise sur un lit honorable, devant lequel a été apprêtée une table, sur laquelle tu as mis mon parfum, et mon huile de senteur.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 Et il y a eu en elle le bruit d'une troupe de gens qui sont à leur aise; et outre ces hommes-là, tant il y a eu de gens, on a fait venir des Sabéens du désert, qui ont mis des bracelets en leurs mains, et des couronnes magnifiques sur leurs têtes.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Et j'ai dit touchant celle qui avait vieilli dans l'adultère: Maintenant ses impudicités prendront fin, et elle aussi.
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 Et toutefois on est venu vers elle, comme on vient vers une femme prostituée; ils sont ainsi venus vers Ahola, et vers Aholiba, femmes [pleines] d'énormité.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 Les hommes justes donc les jugeront comme on juge les femmes adultères, et comme on juge celles qui répandent le sang; car elles sont adultères, et le sang est en leurs mains.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 C'est pourquoi ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: qu'on fasse monter l'assemblée contre elles, et qu'elles soient abandonnées au tumulte et au pillage.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 Et que l'assemblée les assomme de pierres, et les taille en pièces avec leurs épées; qu'ils tuent leurs fils et leurs filles, et qu'ils brûlent au feu leurs maisons.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Et [ainsi] j'abolirai du pays l'énormité, et toutes les femmes seront enseignées à ne faire point selon votre énormité.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 On mettra votre énormité sur vous, et vous porterez les péchés de vos idoles; et vous saurez que je suis le Seigneur l'Eternel.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”

< Ézéchiel 23 >