< Ézéchiel 10 >

1 Puis je regardai, et voici dans l'étendue qui était sur la tête des Chérubins parut au-dessus d'eux comme une pierre de saphir, qui, à la voir, était semblable à un trône.
Mo sì wò ó, mo rí ohun kan tó dàbí òkúta safire nínú òfúrufú tó wà lókè orí kérúbù, ìrísí ohun yìí sì dàbí ìtẹ́.
2 Et on parla à l'homme vêtu de lin, et on lui dit: entre dans l'entre-deux des roues au dessous du Chérubin, et remplis tes paumes de charbons de feu de l'entre-deux des Chérubins, et les répands sur la ville; il y entra donc, moi le voyant.
Olúwa sì sọ fún ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun pé, “Lọ sí àárín àwọn kẹ̀kẹ́ tó wà lábẹ́ kérúbù. Bu ẹyin iná tó kúnwọ́ rẹ láàrín kérúbù, kí o sì fọ́n sórí ìlú náà.” Ó sì lọ lójú mi.
3 Et les Chérubins se tenaient à main droite de la maison quand l'homme entra; et une nuée remplit le parvis intérieur.
Àwọn kérúbù dúró sí apá gúúsù tẹmpili nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ìkùùkuu sì bo inú àgbàlá.
4 Puis la gloire de l'Eternel s'éleva de dessus les Chérubins pour venir sur le seuil de la maison, et la maison fut remplie d'une nuée; le parvis aussi fut rempli de la splendeur de la gloire de l'Eternel.
Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹmpili. Ìkùùkuu sì bo inú tẹmpili, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.
5 Et on entendit le bruit des ailes des Chérubins jusqu'au parvis extérieur, comme la voix du [Dieu] Fort Tout-puissant, quand il parle.
A sì gbọ́ ariwo ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí títí dé àgbàlá tó wà ní ìta gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí Ọlọ́run Olódùmarè bá ń sọ̀rọ̀.
6 Et il arriva que quand il eut commandé à l'homme qui était vêtu de lin, en disant: prends du feu de l'entre-deux des Chérubins; il entra, et se tint auprès des roues.
Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún ọkùnrin aláṣọ funfun yìí pé, “Mú iná láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, láàrín àwọn kérúbù,” ó sì lọ dúró ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ náà.
7 Et l'un des Chérubins étendit sa main vers l'entre-deux des Chérubins au feu qui était dans l'entre-deux des Chérubins; et il en prit, et le mit entre les mains de l'homme vêtu de lin, qui l'ayant reçu, se retira.
Ọ̀kan nínú àwọn kérúbù sì nawọ́ sí ibi iná tó wà láàrín kérúbù yòókù. Ó mú lára rẹ, ó fi sínú ọwọ́ ọkùnrin aláṣọ funfun, òun náà gbà á, ó sì jáde lọ.
8 (Car il apparaissait dans les Chérubins la figure d'une main d'homme sous leurs ailes.)
(Ohun tó dàbí ọwọ́ ènìyàn wà lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí.)
9 Puis je regardai, et voici quatre roues auprès des Chérubins, une roue auprès d'un des Chérubins, et une autre roue auprès d'un Chérubin; et la ressemblance des roues était comme la couleur d'une pierre de chrysolithe.
Nígbà tí mo sì wò, kíyèsí i, àwọn kẹ̀kẹ́ mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kérúbù yìí, kẹ̀kẹ́ kọ̀ọ̀kan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kérúbù kọ̀ọ̀kan; ìrí àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ń tàn yanran bí àwọ̀ òkúta berili.
10 Et quant à leur ressemblance, toutes quatre avaient une même façon, comme si une roue eût été au dedans d'une autre roue.
Ní ti ìrísí wọn, gbogbo wọn jọra wọn; ọ̀kọ̀ọ̀kan rí bí ìgbà tí kẹ̀kẹ́ kan wà nínú kẹ̀kẹ́ mìíràn.
11 Quand elles marchaient, elles allaient sur leurs quatre côtés; et en marchant elles ne se tournaient point, mais au lieu vers lequel le chef tendait, elles allaient après lui; elles ne se tournaient point quand elles marchaient.
Nígbà tí wọ́n ń lọ, wọ́n tẹ̀lé ọ̀kan nínú ọ̀nà mẹ́rin tí àwọn kérúbù dojúkọ; àwọn kẹ̀kẹ́ náà kò yípadà bí àwọn kérúbù ti ń lọ. Àwọn kérúbù ń lọ sí ibi tí orí dojúkọ láì yà.
12 Non plus que tout le corps des Chérubins, ni leur dos, ni leurs mains, ni leurs ailes; et les roues, [savoir] leurs quatre roues, étaient pleines d'yeux à l'entour.
Gbogbo ara wọn àti ẹ̀yìn, ọwọ́ wọn àti ìyẹ́ wọn, àti àwọn kẹ̀kẹ́ kún fún ojú yíkákiri kẹ̀kẹ́, tí àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ní.
13 Et quant aux roues, on les appela, moi l'entendant, un chariot.
Mo gbọ́ tí wọ́n pe àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ni “kẹ̀kẹ́ àjà.”
14 Et chaque [animal] avait quatre faces: la première face était la face d'un Chérubin; et la seconde face [était] la face d'un homme; et la troisième [était] la face d'un lion; et la quatrième la face d'un aigle.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn kérúbù yìí ni ojú mẹ́rin: ojú èkínní jẹ́ ojú kérúbù, ojú kejì jẹ́ ti ènìyàn, ojú kẹta jẹ́ ti kìnnìún nígbà tí ojú kẹrin jẹ́ ti ẹyẹ idì.
15 Puis les Chérubins s'élevèrent en haut. Ce sont là les animaux que j'avais vus auprès du fleuve de Kébar.
A gbé àwọn kérúbù sókè. Èyí ni àwọn ẹ̀dá alààyè tí mo rí létí odò Kebari.
16 Et lorsque les Chérubins marchaient, les roues aussi marchaient auprès d'eux, et quand les Chérubins élevaient leurs ailes pour s'élever de terre, les roues ne se contournaient point d'auprès d'eux.
Bí àwọn kérúbù yìí bá ń lọ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹgbẹ́ wọn náà yóò lọ; bẹ́ẹ̀ ni bí àwọn kérúbù bá tú ìyẹ́ wọn ká láti dìde nílẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ yìí kò ní kúrò lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.
17 Lorsqu'ils s'arrêtaient, elles s'arrêtaient; et lorsqu'ils s'élevaient, elles s'élevaient; car l'esprit des animaux [était] dans les roues.
Bí àwọn kérúbù bá dúró díẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dúró jẹ́ẹ́; bí àwọn kérúbù bá dìde àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dìde, nítorí pé ẹ̀mí àwọn ẹ̀dá alààyè yìí wà nínú wọn.
18 Puis la gloire de l'Eternel se retira de dessus le seuil de la maison, et se tint au dessus des Chérubins.
Ògo Olúwa kúrò níbi ìloro tẹmpili, ó sì dúró sórí àwọn kérúbù.
19 Et les Chérubins élevant leurs ailes, s'élevèrent de terre en ma présence quand ils partirent; et les roues [s'élevèrent] aussi vis-à-vis d'eux, et chacun d'eux s'arrêta à l'entrée de la porte Orientale de la maison de l'Eternel; et la gloire du Dieu d'Israël était sur eux par dessus.
Àwọn kérúbù gbé ìyẹ́ wọn sókè, wọ́n sì fò kúrò nílẹ̀ lójú mi, wọ́n sì lọ pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ wọn lẹ́ẹ̀kan náà. Wọ́n dúró níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn ilé Olúwa, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lórí wọn.
20 Ce sont là les animaux que j'avais vus sous le Dieu d'Israël près du fleuve de Kébar; et je connus que c'étaient des Chérubins.
Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀dá alààyè tí mo rí lábẹ́ Ọlọ́run Israẹli létí odò Kebari, mo sì mọ̀ pé kérúbù ni wọ́n.
21 Chacun avait quatre faces, et chacun quatre ailes, et il y avait une ressemblance de main d'homme sous leurs ailes.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ojú mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin, lábẹ́ ìyẹ́ wọn ni ohun tó jọ ọwọ́ ènìyàn wà.
22 Et quant à la ressemblance de leurs faces, c'étaient les faces que j'avais vues auprès du fleuve de Kébar, et leur [même] regard, et elles-mêmes; et chacun marchait vis-à-vis de soi.
Àfiwé ojú àti ìrísí wọn rí bákan náà pẹ̀lú àwọn tí mo rí létí odò Kebari. Olúkúlùkù wọn sì ń lọ sí ọ̀kánkán tààrà.

< Ézéchiel 10 >