< Exode 35 >

1 Moïse donc assembla toute la congrégation des enfants d'Israël, et leur dit: ce sont ici les choses que l'Eternel a commandé de faire.
Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
2 On travaillera six jours, mais le septième jour il y aura sainteté pour vous; car c'est le Sabbat du repos [consacré] à l'Eternel; quiconque travaillera en ce jour-là, sera puni de mort.
Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
3 Vous n'allumerez point de feu dans aucune de vos demeures le jour du repos.
Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
4 Puis Moïse parla à toute l'assemblée des enfants d'Israël, et leur dit: C'est ici ce que l'Eternel vous a commandé, en disant:
Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
5 Prenez des choses qui sont chez vous, une offrande pour l'Eternel; quiconque sera de bonne volonté, apportera cette offrande pour l'Eternel, [savoir] de l'or, de l'argent, et de l'airain,
Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
6 De la pourpre, de l'écarlate, du cramoisi, et du fin lin, et du poil de chèvres,
aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
7 Des peaux de moutons teintes en rouge, et des peaux de taissons, du bois de Sittim,
awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
8 De l'huile pour le luminaire, des choses aromatiques pour l'huile de l'onction, et pour le parfum composé de choses aromatiques,
òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
9 Des pierres d'Onyx, et des pierres de remplages pour l'Ephod, et pour le Pectoral.
òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
10 Et tous les hommes d'esprit d'entre vous viendront, et feront tout ce que l'Eternel a commandé.
“Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
11 [Savoir], Le pavillon, son Tabernacle, et sa couverture, ses anneaux, ses ais, ses barres, ses piliers, et ses soubassements;
“àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
12 L'Arche et ses barres, le Propitiatoire, et le voile pour tendre au devant;
Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
13 La Table et ses barres, et tous ses ustensiles, et le pain de proposition.
Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
14 Et le chandelier du luminaire, ses ustensiles, ses lampes, et l'huile du luminaire.
Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
15 Et l'autel du parfum et ses barres; l'huile de l'onction, le parfum des choses aromatiques, et la tapisserie pour tendre à l'entrée, [savoir] à l'entrée du pavillon.
Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
16 L'autel de l'holocauste, sa grille d'airain, ses barres et tous ses ustensiles; la cuve, et son soubassement.
Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
17 Les courtines du parvis, ses piliers, ses soubassements, et la tapisserie pour tendre à la porte du parvis.
Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
18 Et les pieux du pavillon, et les pieux du parvis, et leur cordage.
Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
19 Les vêtements du service, pour faire le service dans le Sanctuaire, les saints vêtements d'Aaron Sacrificateur, et les vêtements de ses fils pour exercer la Sacrificature.
Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
20 Alors toute l'assemblée des enfants d'Israël sortit de la présence de Moïse.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
21 Et quiconque fut ému en son cœur, quiconque, [dis-je], se sentit porté à la libéralité, apporta l'offrande de l'Eternel pour l'ouvrage du Tabernacle d'assignation, et pour tout son service, et pour les saints vêtements.
olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
22 Et les hommes vinrent avec les femmes; quiconque fut de cœur volontaire, apporta des boucles, des bagues, des anneaux, des bracelets, et des joyaux d'or, et quiconque offrit quelque offrande d'or à l'Eternel.
Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
23 Tout homme aussi chez qui se trouvait de la pourpre, de l'écarlate, du cramoisi, du fin lin, du poil de chèvres, des peaux de moutons teintes en rouge, et des peaux de taissons, [les] apporta.
Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
24 Tout homme qui avait de quoi faire une offrande d'argent, et d'airain, l'apporta pour l'offrande de l'Eternel; tout homme aussi chez qui fut trouvé du bois de Sittim pour tout l'ouvrage du service, l'apporta.
Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
25 Toute femme adroite, fila de sa main, et apporta ce qu'elle avait filé, de la pourpre, de l'écarlate, du cramoisi, et du fin lin.
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
26 Toutes les femmes aussi dont le cœur les porta [à travailler] de leur industrie, filèrent du poil de chèvre.
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
27 Les principaux aussi [de l'assemblée] apportèrent des pierres d'Onyx, et des pierres de remplages pour l'Ephod et pour le Pectoral;
Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
28 Et des choses aromatiques, et de l'huile, tant pour le luminaire, que pour l'huile de l'onction, et pour le parfum composé de choses aromatiques.
Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
29 Tout homme donc et toute femme que leur cœur incita à la libéralité, pour apporter de quoi faire l'ouvrage que l'Eternel avait commandé par le moyen de Moïse qu'on fît, tous les enfants, [dis-je], d'Israël apportèrent volontairement des présents à l'Eternel.
Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
30 Alors Moïse dit aux enfants d'Israël: voyez, l'Eternel a appelé par son nom Betsaléel, fils d'Uri, fils de Hur, de la Tribu de Juda;
Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
31 Et il l'a rempli de l'Esprit de Dieu en sagesse, en intelligence, en science, pour toute sorte d'ouvrages.
Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
32 Même afin d'inventer des dessins pour travailler en or, en argent, en airain;
Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
33 Dans la sculpture des pierres précieuses pour les mettre en œuvre; et dans la menuiserie, pour travailler en tout ouvrage exquis.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
34 Et il lui a mis aussi au cœur, tant à lui qu'à Aholiab fils d'Ahisamac, de la Tribu de Dan, de l'enseigner;
Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
35 Et il les a remplis d'industrie pour faire toute sorte d’ouvrages d'ouvrier, même d'ouvrier en ouvrage exquis, et en broderie, en pourpre, en écarlate, en cramoisi, et en fin lin, et [d'ouvrage] de tissure, faisant toute sorte d'ouvrages, et inventant [toute sorte] de dessins.
Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.

< Exode 35 >