< Amos 4 >

1 Ecoutez cette parole-ci, vaches de Basan, qui [vous tenez] dans la montagne de Samarie, qui faites tort aux chétifs, et qui opprimez les pauvres; qui dites à leurs seigneurs: Apportez, et que nous buvions.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 Le Seigneur l'Eternel a juré par sa sainteté, que voici, les jours viennent sur vous qu'il vous enlèvera sur des boucliers; et ce qui restera de vous, avec des hameçons de pêche.
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 Et vous sortirez dehors par les brèches, chacune devant soi; et vous jetterez là [ce que vous avez amassé] dans les palais, dit l'Eternel.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Entrez dans Béthel, et y commettez vos crimes; multipliez vos péchés dans Guilgal, et amenez vos sacrifices dès le matin, et vos dîmes au bout de trois ans [accomplis.]
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 Et faites un parfum de pain levé pour l'oblation d'action de grâces; publiez les oblations volontaires, et faites les savoir; car vous l'aimez ainsi, enfants d'Israël, dit le Seigneur l'Eternel.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 C'est pourquoi aussi, je vous ai envoyé la famine en toutes vos villes, et la disette de pain en toutes vos demeures; mais pour cela vous ne vous êtes point retournés jusqu'à moi, dit l'Eternel.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 Je vous ai aussi retenu la pluie, quand il restait encore trois mois jusqu'à la moisson, et j'ai fait pleuvoir sur une ville, et je n'ai point fait pleuvoir sur l'autre; une pièce de terre a été arrosée de pluie, et l'autre pièce, sur laquelle il n'a point plu, est desséchée.
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 Et deux, même trois villes, sont allées vers une ville pour boire de l'eau, et n'ont point été désaltérées, mais pour cela vous ne vous êtes point retournés jusqu'à moi, dit l'Eternel.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 Je vous ai frappés de brûlure, et de nielle; et le hanneton a brouté autant de jardins et de vignes, de figuiers et d'oliviers que vous aviez, mais pour cela vous ne vous êtes point retournés jusqu'à moi, dit l'Eternel.
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 Je vous ai envoyé la mortalité, de la manière que je l'avais envoyée en Egypte, et j'ai fait mourir par l'épée vos gens d'élite, et vos chevaux qui avaient été pris, et j'ai fait monter la puanteur de vos camps même en vos narines, mais pour cela vous ne vous êtes point retournés jusqu'à moi, dit l'Eternel.
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 J'en ai renversé d'entre vous en la manière que Dieu renversa Sodome et Gomorrhe, et vous avez été comme un tison arraché du feu, mais pour cela vous ne vous êtes point retournés jusqu'à moi, dit l'Eternel,
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 C'est pourquoi je te traiterai ainsi, ô Israël! et parce que je te ferai ceci, prépare-toi à la rencontre de ton Dieu, ô Israël!
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 Car voici, celui qui a formé les montagnes, et qui a créé le vent, et qui déclare à l'homme quelle est sa pensée, qui fait l'aube [et] l'obscurité, et qui marche sur les lieux hauts de la terre; l'Eternel Dieu des armées est son Nom.
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

< Amos 4 >