< 2 Rois 25 >
1 Il arriva donc la neuvième année du règne de Sédécias, le dixième jour du dixième mois, que Nébucadnetsar Roi de Babylone vint avec toute son armée contre Jérusalem, et se campa contr'elle, et ils bâtirent des forts tout autour.
Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ìjọba Sedekiah. Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli yan lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ogun rẹ̀. Ó sì pàgọ́ sí ìta ìlú ó sì mu àwọn iṣẹ́ ìdọ̀tí fi yí gbogbo rẹ̀ ká.
2 Et la ville fut assiégée jusqu'à la onzième année du Roi Sédécias.
Ìlú náà sì wà ní ìhámọ́ lábẹ́ ìgbóguntì títí di ọdún kọkànlá ti ọba Sedekiah.
3 Et le neuvième jour du [quatrième] mois la famine augmenta dans la ville, de sorte qu'il n'y avait point de pain pour le peuple du pays.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹsànán oṣù kẹrin, ìyàn tí mú ní ìlú tí ó jẹ́ wí pé kò sí oúnjẹ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.
4 Alors la brèche fut faite à la ville, et tous les gens de guerre [s'enfuirent] de nuit par le chemin de la porte entre les deux murailles qui [étaient] près du jardin du Roi (or les Caldéens [étaient tout] joignant la ville à l'environ) et le Roi s'en alla par le chemin de la campagne.
Nígbà náà odi ìlú náà sì fọ́nká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun sálọ ní òru láti ẹnu-ọ̀nà bodè láàrín ògiri méjì ní ẹgbẹ́ ọgbà ọba, àwọn ará Babeli wọ́n sì yí ìlú náà ká. Wọ́n sálọ sí ìkọjá Arabah.
5 Mais l'armée des Caldéens poursuivit le Roi, et quand ils l'eurent atteint dans les campagnes de Jérico, toute son armée se dispersa d'auprès de lui.
Ṣùgbọ́n ogun àwọn ará Kaldea sì lépa ọba, wọ́n sì lé e bá ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì yà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì túká,
6 Ils prirent donc le Roi, et le firent monter vers le Roi de Babylone à Ribla; où on lui fit son procès.
wọ́n sì mú un. Wọ́n sì mú lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli ní Ribla, níbi tí à ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.
7 Et on égorgea les fils de Sédécias en sa présence; après quoi on creva les yeux à Sédécias, et l'ayant lié de doubles chaînes d'airain, on le mena à Babylone.
Wọ́n sì pa ọmọ Sedekiah níwájú rẹ̀, wọ́n sì yọ ojú rẹ̀ jáde, wọn dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n idẹ wọ́n sì gbe é lọ sí Babeli.
8 Et au septième [jour] du cinquième mois, en la dix-neuvième année du Roi Nébucadnetsar, Roi de Babylone, Nébuzar-adan prévôt de l'hôtel, serviteur du Roi de Babylone, entra dans Jérusalem;
Ní ọjọ́ keje ní oṣù karùn-ún, ní ọdún kọkàndínlógún ti Nebukadnessari ọba Babeli, Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́, ìránṣẹ́ ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu;
9 Et il brûla la maison de l'Eternel, et la maison Royale, et toutes les maisons de Jérusalem, et mit le feu dans toutes les maisons des Grands.
ó sì finá sí ilé Olúwa, ilé ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà ní Jerusalẹmu àti gbogbo ilé ńlá ńlá ni ó dáná sun.
10 Et toute l'armée des Caldéens, qui [était] avec le prévôt de l'hôtel, démolit les murailles de Jérusalem tout autour.
Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀.
11 Et Nébuzar-adan prévôt de l'hôtel transporta [à Babylone] le reste du peuple, [savoir] ceux qui étaient demeurés de reste dans la ville, et ceux qui s'étaient allés rendre au Roi de Babylone, et le reste de la multitude.
Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà.
12 Néanmoins le prévôt de l'hôtel laissa quelques-uns des plus pauvres du pays pour [être] vignerons et laboureurs.
Ṣùgbọ́n olórí ẹ̀ṣọ́ fi àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa bojútó àjàrà àti láti máa ṣe aroko.
13 Et les Caldéens mirent en pièces les colonnes d'airain qui [étaient] dans la maison de l'Eternel, et les soubassements, et la mer d'airain qui [était] dans la maison de l'Eternel, et ils en emportèrent l'airain à Babylone.
Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, wọ́n sì kó idẹ náà lọ sí Babeli.
14 Ils emportèrent aussi les chaudrons, et les racloirs, et les serpes, et les tasses, et tous les ustensiles d'airain dont on faisait le service.
Wọ́n sì kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, síbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ wọ̀n-ọn-nì tí wọ́n fi ṣiṣẹ́ lọ.
15 Le prévôt de l'hôtel emporta aussi les encensoirs et les bassins; et ce qui était d'or, et ce qui était d'argent.
Olórí ẹ̀ṣọ́ kó ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, àti ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, èyí tí wọ́n fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.
16 Quant aux deux colonnes, à la mer, et aux soubassements que Salomon avait faits pour la maison de l'Eternel, on ne pesa point l'airain de tous ces vaisseaux.
Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan, àti ìjókòó wọ̀n-ọn-nì tí Solomoni ti ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èló wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lé wọ́n lọ.
17 Chaque colonne avait dix-huit coudées de haut, et elle avait un chapiteau d'airain par dessus, dont la hauteur était de trois coudées, outre le rets et les grenades qui étaient autour du chapiteau, le tout d'airain; et la seconde colonne était de même façon, avec le rets.
Gíga ọ̀wọ́n kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún, àti ọnà-orí rẹ̀ idẹ ni: àti gíga ọnà-orí náà ni ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta; àti iṣẹ́ híhun náà, àti àwọn pomegiranate tí ó wà lórí ọnà-orí náà yíká, gbogbo rẹ̀ ti idẹ ni: gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́n yìí sì ni ọ̀wọ́n kejì pẹ̀lú iṣẹ́ híhun.
18 Le prévôt de l'hôtel emmena aussi Séraja premier Sacrificateur, et Sophonie second Sacrificateur, et les trois gardes des vaisseaux.
Olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ sì mú gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, Seraiah olórí àwọn àlùfáà, Sefaniah àlùfáà kejì, àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta.
19 Il emmena aussi de la ville un Eunuque qui avait la charge des hommes de guerre, et cinq hommes de ceux qui voyaient la face du Roi, lesquels furent trouvés dans la ville. [Il emmena] aussi le Secrétaire du Capitaine de l'armée qui enrôlait le peuple du pays, et soixante hommes d'entre le peuple du pays, qui furent trouvés dans la ville.
Àti àwọn tí ó kù ní ìlú, ó mú ìwẹ̀fà kan tí ó fi se olórí àwọn ológun, àti ọkùnrin márùn-ún nínú àwọn tó ń gba ọba ní ìmọ̀ràn. Ó sì tún mú akọ̀wé olórí ogun, tí ó ń to àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti ọgọ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú.
20 Nébuzar-adan donc prévôt de l'hôtel les prit, et les mena au Roi de Babylone à Ribla.
Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla.
21 Et le Roi de Babylone les frappa, et les fit mourir à Ribla, au pays de Hamath; ainsi Juda fut transporté hors de sa terre.
Níbẹ̀ ní Ribla, ní ilẹ̀ Hamati, ọba Babeli sì kọlù wọ́n. Bẹ́ẹ̀ ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
22 Mais quant au peuple qui était demeuré de reste au pays de Juda, [et] que Nébucadnetsar Roi de Babylone y avait laissé, il établit pour Gouverneur sur eux Guédalia fils d'Ahikam, fils de Saphan.
Nebukadnessari ọba Babeli ó mú Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani, láti jẹ baálẹ̀ lórí àwọn ènìyàn tí ó kù sílẹ̀ ní ilẹ̀ Juda.
23 Quand tous les Capitaines des gens de guerre, et leurs gens, eurent appris que le Roi de Babylone avait établi Guédalia pour Gouverneur, ils allèrent trouver Guédalia à Mitspa, [savoir]Ismaël fils de Néthania, et Johanan fils de Karéath, et Séraja fils de Tanhumeth Nétophathite, Jaazania fils d'un Mahachathite, eux et leurs gens.
Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ọkùnrin wọn gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ni Mispa. Iṣmaeli ọmọ Netaniah, Johanani ọmọ Karea, Seraiah ọmọ Tanhumeti ará Netofa, Jaaṣaniah ọmọ ará Maakati, àti àwọn ọkùnrin wọn.
24 Et Guédalia leur jura et à leurs gens, et leur dit: Ne faites pas difficulté d'être serviteurs des Caldéens; demeurez au pays, et servez le Roi de Babylone, et vous vous en trouverez bien.
Gedaliah sì búra láti fi dá àwọn ènìyàn rẹ̀ lójú. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn ìjòyè ará Babeli,” ó wí pé, “Ẹ máa gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.”
25 Mais il arriva au septième mois, qu'Ismaël fils de Néthania, fils d'Elisamah, qui était du sang Royal, et dix hommes avec lui vinrent, et frappèrent Guédalia, dont il mourut. [Ils frappèrent] aussi les Juifs et les Caldéens qui étaient avec lui à Mitspa.
Ní oṣù keje, ni Iṣmaeli ọmọ Netaniah, ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá, ó sì kọlù Gedaliah àti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá ará Juda àti àwọn ará Babeli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Mispa.
26 Et tout le peuple depuis le plus petit jusqu'au plus grand, avec les capitaines des gens de guerre, se levèrent, et s'en allèrent en Egypte, parce qu'ils avaient peur des Caldéens.
Nítorí èyí, gbogbo àwọn ènìyàn láti ẹni kékeré títí dé ẹni ńlá, àti pẹ̀lú àwọn olórí ogun, sálọ si Ejibiti nítorí ẹ̀rù àwọn ará Babeli.
27 Or il arriva la trente-septième année de la captivité de Jéhojachin Roi de Juda, le vingt-septième jour du douzième mois, qu'Evilmérodac, Roi de Babylone, l'année qu'il commença à régner, tira hors de prison Jéhojachin Roi de Juda, et le mit en liberté.
Ní ọdún kẹtàdínlógójì ìgbèkùn Jehoiakini ọba Juda, ní oṣù kejìlá, ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù, Efili-Merodaki ọba Babeli, ní ọdún tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ kúrò nínú túbú.
28 Et il lui parla avec douceur, et mit son trône au dessus du trône des Rois qui étaient avec lui à Babylone.
Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli.
29 Et après qu'il lui eut changé ses vêtements de prison, il mangea du pain ordinairement tout le temps de sa vie en sa présence.
Ó sì pàrọ̀ àwọn aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
30 Et quant à son ordinaire, un ordinaire continuel lui fut établi par le Roi chaque jour, tout le temps de sa vie.
Ní ojoojúmọ́, ọba fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè.