< 2 Rois 23 >

1 Alors le Roi envoya, et on assembla vers lui tous les Anciens de Juda et de Jérusalem.
Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
2 Et le Roi monta à la maison de l'Eternel, et avec lui tous les hommes de Juda, et tous les habitants de Jérusalem, et les Sacrificateurs et les Prophètes, et tout le peuple, depuis le plus petit jusqu'au plus grand, et on lut, eux l'entendant, toutes les paroles du Livre de l'alliance, qui avait été trouvé dans la maison de l'Eternel.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
3 Et le Roi se tint auprès de la colonne, et traita devant l'Eternel cette alliance-ci, qu'ils suivraient l'Eternel, et qu'ils garderaient de tout leur cœur, et de toute leur âme, ses commandements, ses témoignages, et ses statuts, pour persévérer dans les paroles de cette alliance, écrites dans ce Livre; et tout le peuple se tint à cette alliance.
Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
4 Alors le Roi commanda à Hilkija le grand Sacrificateur, et aux Sacrificateurs du second rang, et à ceux qui gardaient les vaisseaux, de tirer hors du Temple de l'Eternel tous les ustensiles qui avaient été faits pour Bahal, et pour les bocages, et pour toute l'armée des cieux; et il les brûla hors de Jérusalem dans les champs de Cédron, et on emporta leur poudre à Béthel.
Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
5 Et il abolit les prêtres des idoles, que les Rois de Juda avaient établis quand on faisait des encensements dans les hauts lieux, dans les villes de Juda, et autour de Jérusalem; il [abolit] aussi ceux qui faisaient des encensements à Bahal; au soleil, à la lune, et aux astres, à toute l'armée des cieux.
Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
6 Il fit aussi emporter le bocage de la maison de l'Eternel hors de Jérusalem, en la vallée de Cédron, et le brûla dans la vallée de Cédron; il le réduisit en poudre, et le jeta sur le sépulcre des enfants du peuple.
Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
7 Ensuite il démolit les maisons des prostitués à paillardise, lesquelles étaient dans la maison de l'Eternel; [et] dans lesquelles les femmes travaillaient à faire des pavillons pour le bocage.
Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
8 Il fit aussi venir des villes de Juda tous les Sacrificateurs, et profana les hauts lieux où les Sacrificateurs avaient fait des encensements, depuis Guébah jusqu'à Béer-sebah; et il démolit les hauts lieux des portes qui étaient à l'entrée de la porte de Josué, capitaine de la ville, laquelle est à la gauche de la porte de la ville.
Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
9 Au reste, ceux qui avaient été Sacrificateurs des hauts lieux ne montaient point vers l'autel de l'Eternel à Jérusalem, mais ils mangeaient des pains sans levain parmi leurs frères.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
10 Il profana aussi Topheth, qui était dans la vallée du fils de Hinnom, afin qu'il ne servît plus à personne pour y faire passer son fils ou sa fille par le feu, à Molec.
Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
11 Il ôta aussi de l'entrée de la maison de l'Eternel les chevaux que les Rois de Juda avaient consacrés au soleil, vers le logis de Néthanmélec Eunuque, situé à Parvarim, et il brûla au feu les chariots du soleil.
Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
12 Le Roi démolit aussi les autels qui étaient sur le toit de la chambre haute d'Achaz, que les Rois de Juda avaient faits, et les autels que Manassé avait faits dans les deux parvis de la maison de l'Eternel; il les brisa, les ôtant de là, et il en répandit la poudre au torrent de Cédron.
Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
13 Le Roi profana aussi les hauts lieux qui étaient vis-à-vis de Jérusalem à la main droite sur la montagne des oliviers, [que] Salomon Roi d'Israël avait bâtis à Hastareth, l'abomination des Sidoniens; et à Kémos, l'abomination des Moabites; et à Milkom, l'abomination des enfants de Hammon.
Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
14 Il brisa aussi les statues, et coupa les bocages, et remplit d'ossements d'hommes les lieux ou ils étaient.
Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
15 Il démolit aussi l'autel qui était à Bethel, [et] le haut lieu qu'avait fait Jéroboam fils de Nébat, qui avait fait pécher Israël, cet autel-là, dis-je, et le haut lieu; il brûla le haut lieu, et le réduisit en poudre, et brûla le bocage.
Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
16 Or Josias s'étant tourné, avait vu les sépulcres qui étaient là en la montagne, et il avait envoyé prendre les os des sépulcres, et les avait brûlés sur l'autel, et il l'avait ainsi profané, suivant la parole de l'Eternel, que l'homme de Dieu avait prononcée à haute voix, lorsqu'il prononça ces choses-là à haute voix.
Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
17 Et le Roi avait dit: Qu'est-ce que ce tombeau que je vois? Et les hommes de la ville lui avaient répondu: C'est le sépulcre de l'homme de Dieu qui vint de Juda, et qui prononça à haute voix les choses que tu as faites sur l'autel de Bethel.
Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
18 Et il avait dit: Laissez-le, que personne ne remue ses os; ainsi ils avaient préservé ses os, avec les os du Prophète qui était venu de Samarie.
“Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
19 Josias ôta aussi toutes les maisons des hauts lieux qui étaient dans les villes de Samarie, que les Rois d'Israël avaient faites pour irriter [l'Eternel]; et il leur fit selon tout ce qu'il avait fait à Bethel.
Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
20 Et il sacrifia sur les autels tous les sacrificateurs des hauts lieux qui étaient là, et brûla sur eux des ossements d'hommes; puis il s'en retourna à Jérusalem.
Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
21 Alors le Roi commanda à tout le peuple, en disant: Célébrez la Pâque à l'Eternel votre Dieu, en la manière qu'il est écrit au Livre de cette alliance.
Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
22 Et certainement jamais Pâque ne fut célébrée dans le temps des Juges qui avaient jugé en Israël, ni dans tout le temps des Rois d'Israël, et des Rois de Juda,
Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
23 Comme cette Pâque qui fut célébrée en l'honneur de l'Eternel dans Jérusalem, la dix-huitième année du Roi Josias.
Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
24 Josias extermina aussi ceux qui avaient des esprits de Python, les diseurs de bonne aventure, les Théraphims, les dieux de fiente, et toutes les abominations qui avaient été vues dans le pays de Juda, et dans Jérusalem; afin d'accomplir les paroles de la Loi, écrites au livre qu' Hilkija le Sacrificateur avait trouvé dans la maison de l'Eternel.
Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
25 Avant lui il n'y eut point de Roi qui lui fut semblable, qui se retournât vers l'Eternel de tout son cœur, et de toute son âme, et de toute sa force; selon toute la Loi de Moïse; et après lui il ne s'en est point levé de semblable à lui.
Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
26 Toutefois l'Eternel ne revint point de l'ardeur de sa grande colère de laquelle il avait été embrasé contre Juda, à cause de tout ce que Manassé avait fait pour l'irriter.
Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
27 Car l'Eternel avait dit: Je rejetterai aussi Juda de devant ma face, comme j'ai rejeté Israël; et je rejetterai cette ville de Jérusalem, que j'ai choisie, et la maison de laquelle j'ai dit: Mon nom sera là.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
28 Le reste des faits de Josias, tout ce, dis-je, qu'il a fait, n'est-il pas écrit au Livre des Chroniques des Rois de Juda?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
29 De son temps, Pharaon-Néco Roi d'Egypte monta contre le Roi des Assyriens vers le fleuve d'Euphrate, et Josias s'en alla au devant de lui, mais dès que Pharaon l'eut vu, il le tua à Méguiddo.
Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
30 Et ses serviteurs le chargèrent mort sur un chariot de Méguiddo, et le portèrent à Jérusalem, et l'ensevelirent dans son sépulcre; et le peuple du pays prit Jéhoachaz, fils de Josias, et ils l'oignirent, et l'établirent Roi en la place de son père.
Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
31 Jéhoachaz était âgé de vingt et trois ans, quand il commença à régner, et il régna trois mois à Jérusalem; sa mère avait nom Hamutal, fille de Jérémie de Libna.
Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
32 Il fit ce qui déplaît à l'Eternel, comme avaient fait ses pères.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
33 Et Pharaon-Néco l'emprisonna à Ribla, au pays de Hamath, afin qu'il ne régnât plus à Jérusalem; et il imposa sur le pays une amende de cent talents d'argent, et d'un talent d'or.
Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
34 Puis Pharaon-Néco établit pour Roi Eliakim fils de Josias, en la place de Josias son père, et lui changea son nom, [l'appelant] Jéhojakim; et il prît Jéhoachaz, qui vint en Egypte, où il mourut.
Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
35 Or Jéhojakim donna cet argent et cet or à Pharaon, ayant mis des taxes sur le pays pour fournir cet argent selon le commandement de Pharaon; [et] il leva l'argent et l'or de chacun du peuple du pays selon qu'il était taxé, pour donner à Pharaon-Néco.
Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
36 Jéhojakim était âgé de vingt-cinq ans quand il commença à régner, et il régna onze ans à Jérusalem; sa mère avait nom Zebudda, fille de Pédaja de Ruma.
Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
37 Il fit ce qui déplaît à l'Eternel, comme avaient fait ses pères.
Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.

< 2 Rois 23 >