< 2 Chroniques 9 >
1 Or la reine de Séba ayant ouï parler de la renommée de Salomon, vint à Jérusalem, pour éprouver Salomon par des questions obscures, ayant un fort grand train, et des chameaux qui portaient des choses aromatiques, et une grande quantité d'or, et de pierres précieuses; et étant venue auprès de Salomon, elle lui parla de tout ce qu'elle avait en son cœur.
Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ nípa òkìkí Solomoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè tí ó le. Ó dé pẹ̀lú ẹgbẹ́ ńlá kan pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye wúrà, àti òkúta iyebíye, ó wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni ó sì sọ̀rọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ nípa gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn rẹ̀.
2 Et Salomon lui expliqua tout ce qu'elle avait proposé, en sorte qu'il n'y eut rien que Salomon n'entendît, et qu'il ne lui expliquât.
Solomoni sì dá a lóhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyíkéyìí tí kò lè ṣe àlàyé fún.
3 Et la reine de Séba voyant la sagesse de Salomon, et la maison qu'il avait bâtie,
Nígbà tí ayaba Ṣeba rí ọgbọ́n Solomoni àti pẹ̀lú ilé tí ó ti kọ́,
4 Et les mets de sa table, les logements de ses serviteurs, l'ordre du service de ses officiers, leurs vêtements, ses échansons, et leurs vêtements, et la montée par laquelle il montait dans la maison de l'Eternel, fut toute ravie hors d'elle-même.
oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì rẹ̀, àti ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti dídúró àwọn ìránṣẹ́ nínú aṣọ wọn, àti àwọn agbọ́tí nínú aṣọ wọn àti ẹbọ sísun tí ó ṣe ní ilé Olúwa, ó sì dá a lágara fún ìyàlẹ́nu.
5 Et elle dit au Roi: Ce que j'ai ouï dire dans mon pays de ton état et de ta sagesse, est véritable.
Ó sì wí fún ọba pé, “Ìròyìn tí mo gbọ́ ní ìlú mi nípa iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ, òtítọ́ ni.
6 Et je n'ai point cru ce qu'on en disait, jusqu'à ce que je suis venue, et que mes yeux l'ont vu, et voici, on ne m'avait pas rapporté la moitié de la grandeur de ta sagesse; tu surpasses le bruit que j'en avais ouï.
Ṣùgbọ́n èmi kò gba ohun tí wọ́n sọ gbọ́ àyàfi ìgbà tí mó dé ibí tí mo sì ri pẹ̀lú ojú mi. Nítòótọ́, kì í tilẹ̀ ṣe ìdájọ́ ìdajì títóbi ọgbọ́n rẹ ní a sọ fún mi: ìwọ ti tàn kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
7 Ô que bienheureux sont tes gens! ô que bienheureux sont tes serviteurs qui se tiennent continuellement devant toi, et qui entendent les paroles de ta sagesse!
Báwo ni inú àwọn ọkùnrin rẹ ìbá ṣe dùn tó! Báwo ní dídùn inú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn tí n dúró nígbà gbogbo níwájú rẹ láti gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
8 Béni soit l'Eternel ton Dieu, qui t'a eu pour agréable, en te mettant sur son trône, afin que tu sois Roi pour l'Eternel ton Dieu! Parce que ton Dieu aime Israël, pour le faire subsister à toujours, il t'a établi Roi sur eux, afin que tu exerces le jugement et la justice.
Ìyìn ló yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ní inú dídùn nínú rẹ tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀ láti jẹ ọba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run rẹ fún Israẹli láti fi ìdí wọn kalẹ̀ láéláé, ó sì ti fi ọ́ ṣe ọba lórí wọn, láti ṣe ìdájọ́ àti òtítọ́.”
9 Puis elle donna au Roi six vingts talents d'or, et des choses aromatiques en abondance, et des pierres précieuses; et jamais il n'y eut depuis cela de telles choses aromatiques, que celles que la reine de Séba donna au Roi Salomon.
Nígbà náà ni ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye tùràrí, àti òkúta iyebíye. Kò sì tí ì sí irú tùràrí yí gẹ́gẹ́ bí èyí tí ayaba Ṣeba fi fún ọba Solomoni.
10 Et les serviteurs de Hiram, et les serviteurs de Salomon, qui avaient apporté de l'or d'Ophir, apportèrent du bois d'Algummim, et des pierres précieuses.
Àwọn ènìyàn Hiramu àti àwọn ọkùnrin Solomoni gbé wúrà wá láti Ofiri, wọ́n sì tún gbé igi algumu pẹ̀lú àti òkúta iyebíye wá.
11 Et le Roi fit de ce bois d'Algummim les chemins qui allaient à la maison de l'Eternel, et à la maison Royale, et des violons et des musettes pour les chantres. On n'avait point vu de ce bois auparavant dans le pays de Juda.
Ọba sì lo igi algumu náà láti fi ṣe àtẹ̀gùn fún ilé Olúwa àti fún ilé ọba àti láti fi ṣe dùùrù àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Kò sì ṣí irú rẹ̀ tí a ti rí rí ní ilẹ̀ Juda.
12 Et le Roi Salomon donna à la reine de Séba tout ce qu'elle souhaita, et tout ce qu'elle lui demanda, excepté de ce qu'elle avait apporté au Roi. Puis elle s'en retourna, et revint en son pays, elle et ses serviteurs.
Ọba Solomoni fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ohun tí ó béèrè fún àti ohun tí ó wù ú; ó sì fi fún un ju èyí tí ó mú wá fún un lọ. Nígbà náà ni ó lọ ó sì padà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìlú rẹ̀.
13 Le poids de l'or qui revenait chaque année à Salomon, était de six cent soixante et six talents d'or;
Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì,
14 Sans [ce qui lui revenait] des facteurs des marchands en gros, et [sans ce que lui] apportaient les marchands qui vendaient en détail, et tous les Rois d'Arabie, et les Gouverneurs de ces pays-là, qui apportaient de l'or et de l'argent à Salomon.
láì tí ì ka àkójọpọ̀ owó ìlú tí ó wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn oníṣòwò àti àwọn ọlọ́jà. Àti pẹ̀lú gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀ náà mu wúrà àti fàdákà wá fún Solomoni.
15 Le Roi Salomon fit aussi deux cents grands boucliers d'or étendu au marteau, employant pour chaque bouclier six cents [pièces] d'or étendu au marteau;
Ọba Solomoni sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì tí a fi òlùlù wúrà sí ọ̀kánkán asà.
16 Et trois cents [autres] boucliers d'or étendu au marteau, employant trois cents pièces d'or pour chaque bouclier; et le Roi les mit dans la maison du parc du Liban.
Ó sì ti ṣe ọ̀ọ́dúnrún kékeré ṣékélì tí a fi òlùlù wúrà, pẹ̀lú ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì wúrà nínú àpáta kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sínú ààfin ti ó wà ní igbó Lebanoni.
17 Le Roi fit aussi un grand trône d'ivoire, qu'il couvrit de pur or.
Nígbà náà ọba sì ṣe ìtẹ́ pẹ̀lú eyín erin ńlá kan ó sì fi wúrà tó mọ́ bò ó.
18 Et ce trône avait six degrés, et un marche-pied d'or, fait en pente, et le tout tenait au trône, et des accoudoirs de côté et d'autre à l'endroit du siège; et deux lions étaient près des accoudoirs.
Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, àti pẹ̀lú àpótí ìtìsẹ̀ wúrà kan ni a dè mọ́ ọn. Ní ìhà méjèèjì ibi ìjókòó ní ó ní ìgbọ́wọ́lé, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́bàá olúkúlùkù wọn.
19 Il y avait aussi douze lions sur les six degrés du trône de côté et d'autre; il ne s'en était point fait de tel dans aucun Royaume.
Kìnnìún méjìlá dúró lórí àtẹ̀gùn mẹ́ta, ọ̀kan àti ní ìhà olúkúlùkù àtẹ̀gùn kò sì sí irú rẹ̀ tí a ti ṣe rí fún ìjọba mìíràn.
20 Et toute la vaisselle du buffet du Roi Salomon était d'or, et tous les vaisseaux de la maison du parc du Liban étaient de fin or. Il n'y en avait point d'argent; l'argent n'était rien estimé aux jours de Salomon.
Gbogbo ohun èlò mímú ìjọba Solomoni ọba ni ó jẹ́ kìkì wúrà, àti gbogbo ohun èlò ààfin ní igbó Lebanoni ni ó jẹ́ wúrà mímọ́. Kò sì ṣí èyí tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
21 Car les navires du Roi allaient en Tarsis avec les serviteurs de Hiram; et les navires de Tarsis revenaient en trois ans une fois, apportant de l'or, de l'argent, de l'ivoire, des singes, et des paons.
Ọba ní ọkọ̀ tí a fi ń tajà tí àwọn ọkùnrin Hiramu ń bojútó. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ó máa ń padà, ó ń gbé wúrà àti fàdákà àti eyín erin àti ìnàkí.
22 Ainsi le Roi Salomon fut plus grand que tous les Rois de la terre, tant en richesses qu'en sagesse.
Ọba Solomoni sì tóbi nínú ọláńlá àti ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba tí ó kù lórí ilẹ̀ ayé lọ.
23 Et tous les Rois de la terre cherchaient de voir la face de Salomon, pour entendre la sagesse que Dieu avait mise dans son cœur.
Gbogbo àwọn ọba ayé ń wá ojúrere lọ́dọ̀ Solomoni láti gbọ́n ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sínú ọkàn rẹ̀.
24 Et chacun d'eux lui apportait son présent, [savoir] des vaisseaux d'argent, des vaisseaux d'or, des vêtements, des armes et des choses aromatiques, [et lui amenait] des chevaux, et des mulets chaque année.
Ní ọdọọdún, olúkúlùkù ẹni tí o wá mú ẹ̀bùn ohun èlò wúrà àti fàdákà àti aṣọ ìbora, ìhámọ́ra, àti tùràrí, àti ẹṣin àti ìbáaka wá.
25 Salomon avait quatre mille écuries pour des chevaux, et des chariots; et douze mille hommes de cheval, qu'il mit dans les villes où il tenait ses chariots, et auprès du Roi à Jérusalem.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé fún àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, àti ẹgbàá mẹ́fà àwọn ẹṣin, tí ó fi pamọ́ nínú ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ nínú Jerusalẹmu.
26 Et il dominait sur tous les Rois, depuis le fleuve jusqu'au pays des Philistins, et jusqu'à la frontière d'Egypte.
Ó sì jẹ ọba lórí gbogbo àwọn ọba láti odò Eufurate títí dé ilé àwọn ará Filistini àti títí ó fi dé agbègbè ti Ejibiti.
27 Et le Roi fit que l'argent n'était pas plus prisé à Jérusalem que les pierres; et les cèdres, que les figuiers sauvages qui sont dans les plaines, tant il y en avait.
Ọba sì sọ fàdákà dàbí òkúta ní Jerusalẹmu, àti igi kedari ni ó sì ṣe bí igi sikamore, tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
28 Car on tirait d'Egypte des chevaux pour Salomon, et [d'autres choses] de tous les pays.
A sì mú àwọn ẹṣin Solomoni wa láti ilẹ̀ òkèrè láti Ejibiti àti láti gbogbo ìlú.
29 Le reste des faits de Salomon, tant les premiers que les derniers, n'est-il pas écrit au Livre de Nathan le Prophète, et dans la prophétie d'Ahija Silonite, et dans la Vision de Jeddo le Voyant, touchant Jéroboam fils de Nébat?
Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ìjọba Solomoni, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn Natani wòlíì, àti nínú ìsọtẹ́lẹ̀ Ahijah ará Ṣilo àti nínú ìran Iddo, wòlíì tí o so nípa Jeroboamu ọmọ Nebati?
30 Et Salomon régna quarante ans à Jérusalem sur tout Israël.
Solomoni jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo àwọn Israẹli fún ogójì ọdún
31 Puis il s'endormit avec ses pères, et on l'ensevelit en la Cité de David son père, et Roboam son fils régna en sa place.
Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀, Rehoboamu, ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.