< 2 Chroniques 25 >
1 Amatsia commença à régner étant âgé de vingt-cinq ans, et il régna vingt-neuf ans à Jérusalem. Sa mère avait nom Jéhohaddam, [et] elle était de Jérusalem.
Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
2 Il fit ce qui est droit devant l'Eternel; mais non pas d'un cœur parfait.
Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
3 Or il arriva qu'après qu'il fut affermi dans son Royaume, il fit mourir ses serviteurs qui avaient tué le Roi son père.
Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
4 Mais il ne fit point mourir leurs enfants, selon ce qui est écrit dans la Loi, au Livre de Moïse, dans lequel l'Eternel a commandé, en disant: Les pères ne mourront point pour les enfants, et les enfants ne mourront point pour les pères; mais chacun mourra pour son péché.
Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
5 Puis Amatsia assembla ceux de Juda; et les établit selon les familles des pères, selon les capitaines de milliers et de centaines, par tout Juda et Benjamin; et il en fit le dénombrement depuis l'âge de vingt ans, et au dessus; et il s'en trouva trois cent mille d'élite, marchant en bataille, et portant la javeline et le bouclier.
Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
6 Il prit aussi à sa solde cent mille hommes forts et vaillants de ceux d'Israël, pour cent talents d'argent.
Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
7 Mais un homme de Dieu vint à lui, et lui dit: Ô Roi! que l'armée d'Israël ne marche point avec toi, car l'Eternel n'est point avec Israël; ils sont tous enfants d'Ephraïm.
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
8 Sinon, va, fais, fortifie-toi pour la bataille; [mais] Dieu te fera tomber devant l'ennemi; car Dieu a la puissance d'aider et de faire tomber.
Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
9 Et Amatsia répondit à l'homme de Dieu: Mais que deviendront les cent talents que j'ai donnés aux troupes d'Israël? et l'homme de Dieu dit: L'Eternel en a pour t'en donner beaucoup plus.
Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
10 Ainsi Amatsia sépara les troupes qui lui étaient venues d'Ephraïm, afin qu'elles retournassent en leur lieu; et leur colère s'enflamma fort contre Juda, et ils s'en retournèrent en leur lieu avec une grande ardeur de colère.
Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
11 Alors Amatsia ayant pris courage conduisit son peuple, et s'en alla en la vallée du sel; où il battit dix mille hommes des enfants de Séhir.
Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
12 Et les enfants de Juda prirent dix mille hommes vifs, et les ayant amenés sur le sommet d'une roche, ils les jetèrent du haut de la roche, de sorte qu'ils moururent tous.
Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
13 Mais les troupes qu'Amatsia avait renvoyées, afin qu'elles ne vinssent point avec lui à la guerre, se jetèrent sur les villes de Juda, depuis Samarie jusqu'à Béthoron, et tuèrent trois mille hommes, et emportèrent un gros butin.
Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
14 Or il arriva qu'Amatsia étant revenu de la défaite des Iduméens, et ayant apporté les dieux des enfants de Séhir, il se les établit pour dieux; il se prosterna devant eux, et leur fit des encensements.
Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
15 Et la colère de l'Eternel s'enflamma contre Amatsia, et il envoya vers lui un Prophète qui lui dit: Pourquoi as-tu recherché les dieux d'un peuple qui n'ont point délivré leur peuple de ta main?
Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
16 Et comme il parlait au Roi, le Roi lui dit: T'a-t-on établi conseiller du Roi? arrête-toi; pourquoi te ferais-tu tuer? et le Prophète s'arrêta, et lui dit: Je sais très-bien que Dieu a délibéré de te détruire, parce que tu as fait cela, et que tu n'as point obéi à mon conseil.
Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
17 Et Amatsia Roi de Juda, ayant tenu conseil, envoya vers Joas fils de Jéhoachaz, fils de Jéhu, Roi d'Israël, pour [lui] dire: Viens, [et] que nous nous voyions l'un l'autre.
Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
18 Et Joas Roi d'Israël envoya dire à Amatsia Roi de Juda: L'épine qui est au Liban a envoyé dire au cèdre qui est au Liban: Donne ta fille pour femme à mon fils; mais les bêtes sauvages qui sont au Liban, ont passé, et ont foulé l'épine.
Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
19 Tu as dit: Voici, j'ai battu Edom, et ton cœur s'est élevé pour en tirer vanité. Demeure maintenant dans ta maison; pourquoi t'engagerais-tu dans un mal dans lequel tu tomberais, toi et Juda avec toi?
Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
20 Mais Amatsia ne l'écouta point; car cela venait de Dieu, afin de les livrer entre les mains de [Joas], parce qu'ils avaient recherché les dieux d'Edom.
Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
21 Ainsi Joas Roi d'Israël monta, et ils se virent l'un l'autre, lui et Amatsia Roi de Juda, à Beth-sémes, qui est de Juda.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
22 Et Juda ayant été défait par Israël, ils s'enfuirent chacun dans leurs tentes.
Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
23 Et Joas Roi d'Israël prit Amatsia Roi de Juda, fils de Joas, fils de Jéhoachaz, à Beth-sémes; et l'amena à Jérusalem, et il fit une brèche de quatre cents coudées à la muraille de Jérusalem, depuis la porte d'Ephraïm, jusqu'à la porte du coin.
Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
24 Et ayant pris tout l'or et l'argent, et tous les vaisseaux qui furent trouvés dans la maison de Dieu sous la direction d'Hobed-Edom, avec les trésors de la Maison Royale, et des gens pour otages, il s'en retourna à Samarie.
Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
25 Et Amatsia fils de Joas Roi de Juda vécut quinze ans, après que Joas fils de Jéhoachaz Roi d'Israël fut mort.
Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
26 Le reste des faits d'Amatsia, tant les premiers que les derniers, voilà; n'est-il pas écrit au Livre des Rois de Juda et d'Israël?
Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
27 Or depuis le temps qu'Amatsia se fut détourné de l'Eternel, on fit une conspiration contre lui à Jérusalem, et il s'enfuit à Lakis; mais on envoya après lui à Lakis, et on le tua là.
Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
28 Et on l'apporta sur des chevaux, et on l'ensevelit avec ses pères dans la ville de Juda.
A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.