< 2 Chroniques 23 >

1 Mais en la septième année Jéhojadah se fortifia, et prit avec soi des centeniers; [savoir] Hazaria fils de Jéroham, Ismahël fils de Jéhohanan, Hazaria fils de Hobed, Mahaséja fils de Hadaja, Elisaphat fils de Zicri, et traita alliance avec eux.
Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
2 Et ils firent le tour de Juda, et assemblèrent de toutes les villes de Juda les Lévites, et les Chefs des pères d'Israël, et vinrent à Jérusalem.
Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
3 Et toute cette assemblée traita alliance avec le Roi dans la maison de Dieu, et [Jéhojadah] leur dit: Voici, le fils du Roi régnera selon que l'Eternel en a parlé touchant les fils de David.
Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
4 C'est ici [donc] ce que vous ferez: La troisième partie de ceux d'entre vous qui entrerez en semaine, tant des Sacrificateurs, que des Lévites, sera à la porte de Sippim.
Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
5 Et la troisième partie se tiendra vers la maison du Roi; et la troisième partie à la porte du fondement; et que tout le peuple soit dans les parvis de la maison de l'Eternel.
Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
6 Que nul n'entre dans la maison de l'Eternel, que les Sacrificateurs et les Lévites servants; ceux-ci y entreront, parce qu'ils sont sanctifiés; et le reste du peuple fera la garde de l'Eternel.
Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
7 Et ces Lévites-là environneront le Roi tout autour, ayant chacun ses armes en sa main; mais que celui qui entrera dans la maison, soit mis à mort; et tenez-vous auprès du Roi quand il sortira et quand il entrera.
Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
8 Les Lévites donc et tous ceux de Juda firent tout ce que Jéhojadah le Sacrificateur avait commandé, et prirent chacun ses gens, tant ceux qui entraient en semaine que ceux qui sortaient de semaine; car Jéhojadah le Sacrificateur n'avait point donné congé aux départements.
Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
9 Et Jéhojadah le sacrificateur donna aux centeniers des hallebardes, des boucliers, et des rondelles, qui avaient été au Roi David, et qui étaient dans la maison de Dieu.
Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
10 Et il rangea tout le peuple, tout autour du Roi; chacun tenant ses armes en sa main, depuis le côté droit du Temple jusqu'au côté gauche du Temple, tant pour l'autel, que pour le Temple.
Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
11 Alors on amena le fils du Roi, et on mit sur lui la couronne et le témoignage, et ils l'établirent Roi; et Jéhojadah et ses fils l'oignirent, et dirent: Vive le Roi!
Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
12 Et Hathalie entendant le bruit du peuple qui courait, et qui chantait les louanges [de Dieu] autour du Roi, vint vers le peuple en la maison de l'Eternel.
Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
13 Et elle regarda, et voilà, le Roi était près de sa colonne à l'entrée, et les capitaines, et les trompettes étaient près du Roi, et tout le peuple du pays était en joie, et on sonnait des trompettes; les chantres aussi [chantaient] avec des instruments de musique, et montraient comment il fallait chanter les louanges [de Dieu]; et sur cela Hathalie déchira ses vêtements, et dit: Conjuration! conjuration!
Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
14 Alors le Sacrificateur Jéhojadah fit sortir les centeniers, qui avaient la charge de l'armée, et leur dit: Menez-la hors des rangs; et que celui qui la suivra, soit mis à mort par l'épée; car le Sacrificateur avait dit: Ne la mettez point à mort dans la maison de l'Eternel.
Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
15 Ils lui firent donc place; et elle s'en retourna en la maison du Roi par l'entrée de la porte des chevaux, et ils la firent mourir là.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
16 Et Jéhojadah, tout le peuple, et le Roi traitèrent cette alliance, qu'ils seraient le peuple de l'Eternel.
Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
17 Alors tout le peuple entra dans la maison de Bahal, et ils la démolirent; ils brisèrent ses autels et ses images, et tuèrent Mattan Sacrificateur de Bahal, devant les autels.
Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
18 Jéhojadah rétablit aussi les charges de la maison de l'Eternel, entre les mains des Sacrificateurs Lévites, que David avait distribués pour la maison de l'Eternel, afin qu'ils offrissent les holocaustes à l'Eternel, ainsi qu'il est écrit dans la Loi de Moïse, avec joie et avec des cantiques, selon la disposition qui en avait été faite par David.
Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
19 Il établit aussi des portiers aux portes de la maison de l'Eternel; afin qu'aucune personne souillée, pour quelque chose que ce fût, n'y entrât.
Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
20 Il prit [ensuite] les centeniers, les hommes les plus considérables, ceux qui étaient établis en autorité sur le peuple, et tout le peuple du pays; et il fit descendre le Roi de la maison de l'Eternel, et ils entrèrent par le milieu de la haute porte dans la maison du Roi; puis ils firent asseoir le Roi sur le trône Royal.
Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
21 Et tout le peuple du pays fut en joie, et la ville demeura tranquille, bien qu'on eût mis à mort Hathalie par l'épée.
Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.

< 2 Chroniques 23 >