< 2 Chroniques 2 >
1 Or Salomon résolut de bâtir une maison au Nom de l'Eternel, et une Maison Royale.
Solomoni pinnu láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa àti ilé kan fún ìjọba rẹ̀
2 Et il fit un dénombrement de soixante et dix mille hommes qui portaient les faix, et de quatre-vingt mille qui coupaient le bois sur la montagne, et de trois mille six cents qui étaient commis sur eux.
Solomoni sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin àwọn ọkùnrin láti ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ bi olùgé-òkúta ní àwọn òkè àti ẹgbẹ̀rún mẹ́rìndínlógójì gẹ́gẹ́ bí àwọn alábojútó lórí wọn.
3 Et Salomon envoya vers Hiram Roi de Tyr, pour lui dire: Comme tu as fait avec David mon père, et comme tu lui as envoyé des cèdres pour se bâtir une maison afin d'y habiter, [fais-en de même avec moi].
Solomoni rán iṣẹ́ yìí sí Hiramu ọba Tire: “Rán àwọn igi kedari sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe fún baba à mi Dafidi. Nígbà tí ó fi igi kedari ránṣẹ́ sí i láti kọ́ ààfin tí ó ń gbé.
4 Voici, je m'en vais bâtir une maison au Nom de l'Eternel mon Dieu, pour la lui sanctifier, afin de faire fumer devant lui le parfum des odeurs aromatiques, [et lui présenter] les pains de proposition, lesquels on pose continuellement devant lui, et les holocaustes du matin et du soir, pour les Sabbats, et pour les nouvelles lunes, et pour les Fêtes solennelles de l'Eternel notre Dieu; ce qui est perpétuel en Israël.
Nísinsin yìí, èmi n kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi àti láti yà á sí mímọ́ fún un àti láti sun tùràrí olóòórùn dídùn níwájú rẹ̀, fún gbígbé àkàrà ìfihàn ìgbàkúgbà, àti fún ṣíṣe ẹbọ sísun ní gbogbo àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti ní ọjọọjọ́ ìsinmi àti oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn ti Olúwa Ọlọ́run wa. Èyí ni àṣẹ fún Israẹli láéláé.
5 Or la maison que je m'en vais bâtir sera grande; car notre Dieu est grand au dessus de tous les dieux.
“Ilé Olúwa tí èmi yóò kọ́ yóò tóbi, nítorí pé Ọlọ́run wa tóbi ju gbogbo àwọn ọlọ́run mìíràn lọ.
6 Mais qui est-ce qui aura le pouvoir de lui bâtir une maison, si les cieux, même les cieux des cieux ne le peuvent contenir? Et qui suis-je moi, pour lui bâtir une maison, si ce n'est pour faire des parfums devant lui?
Ṣùgbọ́n ta ni ó le è kọ́ ilé fún Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run tó ga jùlọ, kò le è gbà á? Ta ni èmi nígbà náà láti kọ́ ilé fún Olúwa, bí kò ṣe kìkì àti sun ẹbọ sun ẹbọ níwájú rẹ̀?
7 C'est pourquoi envoie-moi maintenant quelque homme qui s'entende à travailler en or, en argent, en airain, en fer, en écarlate, en cramoisi, et en pourpre, et qui sache graver, [afin qu'il soit] avec les hommes experts que j'ai avec moi en Judée, et à Jérusalem, lesquels David mon père a préparés.
“Nítorí náà, rán ọkùnrin kan sí mi, tí a kọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà àti idẹ àti irin, àti ní àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti ní àwọ̀ ojú ọ̀run, tí ó jẹ́ onímọ̀ nínú iṣẹ́ igi gbígbẹ́ láti ṣiṣẹ́ ní Juda àti Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn onímọ̀ oníṣọ̀nà tí baba à mi Dafidi pèsè.
8 Envoie-moi aussi du Liban des bois de cèdre, de sapin, et d'Algummim; car je sais que tes serviteurs s'entendent bien à couper le bois du Liban; et voilà, mes serviteurs [seront] avec les tiens.
“Fi ìtì igi kedari, junifa àti algumu ránṣẹ́ sí mi, láti Lebanoni, nítorí tí mo mọ̀ pé àwọn ọkùnrin rẹ ní ìmọ̀ nínú gígé igi rírẹ́. Àwọn ọkùnrin mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ.
9 Et qu'on m'apprête du bois en grande quantité; car la maison que je m'en vais bâtir [sera] grande, et merveilleuse.
Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nítorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀.
10 Et je donnerai à tes serviteurs qui couperont le bois, vingt mille Cores de froment foulé, vingt mille Cores d'orge, vingt mille Baths de vin, et vingt mille Baths d'huile.
Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin agégi tí ó ń gé ìtì igi náà ni ogún ẹgbẹ̀rún, alikama ilẹ̀ àti ogún ẹgbẹ̀rún, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti barle; ogún ẹgbẹ̀rún, bati ọtí wáìnì àti ogún ẹgbẹ̀rún bati òróró olifi.”
11 Et Hiram, Roi de Tyr, [répondit] par écrit, et manda à Salomon: Parce que l'Eternel a aimé son peuple il t'a établi Roi sur eux.
Hiramu ọba Tire fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Solomoni: “Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti ṣe ọ́ ní ọba wọn.”
12 Et Hiram dit: Béni [soit] l'Eternel le Dieu d'Israël! qui a fait les cieux et la terre, de ce qu'il a donné au Roi David un fils sage, prudent et intelligent, qui doit bâtir une maison à l'Eternel, et une Maison Royale.
Hiramu fi kún un pe, “Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dafidi ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.
13 Je t'envoie donc maintenant un homme expert et habile, [qui a] été à Hiram mon père;
“Èmi ń rán Huramu-Abi, ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye sí ọ.
14 Fils d'une femme issue de la Tribu de Dan, et duquel le père [est] Tyrien, sachant travailler en or, en argent, en airain, en fer, en pierres, et en bois, en écarlate, en pourpre, en fin lin, et en cramoisi; et sachant faire toute sorte de gravure, et de dessin de toutes les choses qu'on lui proposera, avec les hommes d'esprit que tu as, et ceux qu'a eus mon Seigneur David ton père.
Ọmọbìnrin kan nínú àwọn ọmọbìnrin Dani àti tí baba a rẹ̀ wá láti Tire tí ó gbọ́ngbọ́n àti ṣiṣẹ́ ní wúrà àti ní fàdákà, ní idẹ, ní irin, ní òkúta àti ní ìtì igi, ní èse-àlùkò, ní aláró, àti ní ọ̀gbọ̀ tí ó dára, àti òdòdó, láti gbẹ́ onírúurú ohun gbígbẹ́ pẹ̀lú, àti láti ṣe àwárí ìmọ̀ ẹ̀rọ irú ẹ̀yàkẹ́yà tí a ó fún un ṣe. Òun yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n olúwa mi, Dafidi baba a rẹ.
15 Et maintenant que mon Seigneur envoie à ses serviteurs le froment, l'orge, l'huile et le vin qu'il a dit;
“Nísinsin yìí, jẹ́ kí olúwa mi rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní alikama àti barle àti òróró Olifi náà àti ọtí tí ó ti ṣe ìlérí.
16 Et nous couperons du bois du Liban, autant qu'il t'en faudra, et nous te le mettrons par radeaux sur la mer de Japho, et tu les feras monter à Jérusalem.
Àwa yóò sì gé gbogbo àwọn ìtí igi láti Lebanoni tí ìwọ yóò lò pẹ̀lú a ó gbé wọn fò lójú omi òkun lọ sí Joppa. Lẹ́yìn náà ìwọ lè kó wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu.”
17 Salomon donc dénombra tous les hommes étrangers qui [étaient] au pays d'Israël, après le dénombrement que David son père [en] avait fait, et on en trouva cent cinquante-trois mille six cents.
Solomoni ka iye àwọn àjèjì tí ó wà ní Israẹli lẹ́yìn kíka iye wọn tí baba a rẹ̀ Dafidi ti ṣe; a sì ka iye wọn sí ọ̀kẹ́ mẹ́jọ ó dín egbèjìlélọ́gbọ̀n.
18 Et il en établit soixante-dix mille qui portaient les faix, quatre-vingt mille qui coupaient le bois sur la montagne, et trois mille six cents, commis pour faire travailler le peuple.
Ó sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin nínú wọn láti ru ẹrù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin láti ṣe àgọ́ òkúta lórí òkè, àti egbèjìdínlógún alábojútó láti kó àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́.