< 1 Samuel 12 >
1 Alors Samuel dit à tout Israël: Voici, j'ai obéi à votre parole en tout ce que vous m'avez dit, et j'ai établi un Roi sur vous.
Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
2 Et maintenant, voici le Roi qui marche devant vous, car pour moi je suis vieux, et tout blanc de vieillesse, et voici, mes fils aussi sont avec vous; et pour moi j'ai marché devant vous, depuis ma jeunesse jusques à ce jour.
Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
3 Me voici, répondez-moi, devant l'Eternel, et devant son oint. De qui ai-je pris le bœuf? et de qui ai-je pris l'âne? et à qui ai-je fait tort? qui ai-je foulé? et de la main de qui ai-je pris des récompenses, afin d'user de connivence à son égard, et je vous en ferai restitution?
Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
4 Et ils répondirent: Tu ne nous as point opprimés, et tu ne nous as point foulés, et tu n'as rien pris de personne.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
5 Il leur dit encore: L'Eternel est témoin contre vous; son oint aussi est témoin aujourd'hui, que vous n'avez trouvé aucune chose entre mes mains. Et ils répondirent: Il en est témoin.
Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
6 Alors Samuel dit au peuple: L'Eternel est celui qui a fait Moïse et Aaron, et qui a fait monter vos pères hors du pays d'Egypte.
Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
7 Maintenant donc présentez-vous [ici], et j'entrerai en procès contre vous devant l'Eternel, pour tous les bienfaits de l'Eternel, qu'il a faits à vous et à vos pères.
Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
8 Après que Jacob fut entré en Egypte, vos pères crièrent à l'Eternel, et l'Eternel envoya Moïse et Aaron qui tirèrent vos pères hors d'Egypte, et qui les ont fait habiter en ce lieu-ci.
“Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
9 Mais ils oublièrent l'Eternel leur Dieu, et il les livra entre les mains de Siséra, chef de l'armée de Hatsor, et entre les mains des Philistins, et entre les mains du Roi de Moab, qui leur firent la guerre.
“Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
10 Après ils crièrent à l'Eternel, et dirent: Nous avons péché; car nous avons abandonné l'Eternel, et nous avons servi les Bahalins, et Hastaroth. Maintenant donc délivre-nous des mains de nos ennemis, et nous te servirons.
Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
11 Et l'Eternel a envoyé Jerubbahal, et Bedan, et Jephthé, et Samuel, et il vous a délivrés de la main de tous vos ennemis d'alentour, et vous avez habité en pleine assurance.
Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
12 Mais quand vous avez vu que Nahas Roi des enfants de Hammon venait contre vous, vous m'avez dit: Non, mais un Roi régnera sur nous; quoique l'Eternel votre Dieu fût votre Roi.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
13 Maintenant donc voici le Roi que vous avez choisi, que vous avez demandé, et voici l'Eternel l'a établi Roi sur vous.
Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
14 Si vous craignez l'Eternel, et que vous le serviez, et obéissiez à sa voix, et que vous ne soyez point rebelles au commandement de l'Eternel, alors et vous, et votre Roi qui règne sur vous, vous serez sous la conduite de l'Eternel votre Dieu.
Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
15 Mais si vous n'obéissez pas à la voix de l'Eternel, et si vous êtes rebelles au commandement de l'Eternel, la main de l'Eternel sera aussi contre vous, comme elle a été contre vos pères.
ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
16 Or maintenant arrêtez-vous, et voyez cette grande chose que l'Eternel va faire devant vos yeux.
“Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
17 N'est-ce pas aujourd'hui la moisson des blés? Je crierai à l'Eternel, et il fera tonner et pleuvoir; afin que vous sachiez et que vous voyiez, combien le mal que vous avez fait en la présence de l'Eternel est grand, d'avoir demandé un Roi pour vous.
Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
18 Alors Samuel cria à l'Eternel, et l'Eternel fit tonner et pleuvoir en ce jour-là; et tout le peuple craignit fort l'Eternel et Samuel.
Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
19 Et tout le peuple dit à Samuel: Prie pour tes serviteurs l'Eternel ton Dieu, afin que nous ne mourions point; car nous avons ajouté ce mal à tous nos [autres] péchés, d'avoir demandé un Roi pour nous.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
20 Alors Samuel dit au peuple: Ne craignez point; vous avez fait tout ce mal-ci, néanmoins ne vous détournez point d'après l'Eternel, mais servez l'Eternel de tout votre cœur.
Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
21 Ne vous en détournez donc point, car ce serait vous détourner après des choses de néant, qui ne vous apporteraient aucun profit, et qui ne vous délivreraient point; puisque ce sont des choses de néant.
Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
22 Car l'Eternel pour l'amour de son grand Nom n'abandonnera point son peuple; parce que l'Eternel a voulu vous faire son peuple.
Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
23 Et pour moi, Dieu me garde que je pèche contre l'Eternel, et que je cesse de prier pour vous; mais je vous enseignerai le bon et le droit chemin.
Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
24 Seulement craignez l'Eternel, et servez-le en vérité, de tout votre cœur; car vous avez vu les choses magnifiques qu'il a faites pour vous.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
25 Mais si vous persévérez à mal faire, vous serez consumés vous et votre Roi.
Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”