< Psaumes 116 >
1 J’aime l’Éternel, car il entend Ma voix, mes supplications;
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Car il a penché son oreille vers moi; Et je l’invoquerai toute ma vie.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Les liens de la mort m’avaient environné, Et les angoisses du sépulcre m’avaient saisi; J’étais en proie à la détresse et à la douleur. (Sheol )
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol )
4 Mais j’invoquai le nom de l’Éternel: O Éternel, sauve mon âme!
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 L’Éternel est miséricordieux et juste, Notre Dieu est plein de compassion;
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 L’Éternel garde les simples; J’étais malheureux, et il m’a sauvé.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Mon âme, retourne à ton repos, Car l’Éternel t’a fait du bien.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Oui, tu as délivré mon âme de la mort, Mes yeux des larmes, Mes pieds de la chute.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Je marcherai devant l’Éternel, Sur la terre des vivants.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 J’avais confiance, lorsque je disais: Je suis bien malheureux!
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Je disais dans mon angoisse: Tout homme est trompeur.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Comment rendrai-je à l’Éternel Tous ses bienfaits envers moi?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 J’élèverai la coupe des délivrances, Et j’invoquerai le nom de l’Éternel;
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 J’accomplirai mes vœux envers l’Éternel, En présence de tout son peuple.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Elle a du prix aux yeux de l’Éternel, La mort de ceux qui l’aiment.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Écoute-moi, ô Éternel! Car je suis ton serviteur, Ton serviteur, fils de ta servante. Tu as détaché mes liens.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Je t’offrirai un sacrifice d’actions de grâces, Et j’invoquerai le nom de l’Éternel;
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 J’accomplirai mes vœux envers l’Éternel, En présence de tout son peuple,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 Dans les parvis de la maison de l’Éternel, Au milieu de toi, Jérusalem! Louez l’Éternel!
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.