< Josué 12 >
1 Voici les rois que les enfants d’Israël battirent, et dont ils possédèrent le pays de l’autre côté du Jourdain, vers le soleil levant, depuis le torrent de l’Arnon jusqu’à la montagne de l’Hermon, avec toute la plaine à l’orient.
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sihon, roi des Amoréens, qui habitait à Hesbon. Sa domination s’étendait depuis Aroër, qui est au bord du torrent de l’Arnon, et, depuis le milieu du torrent, sur la moitié de Galaad, jusqu’au torrent de Jabbok, frontière des enfants d’Ammon;
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 sur la plaine, jusqu’à la mer de Kinnéreth à l’orient, et jusqu’à la mer de la plaine, la mer Salée, à l’orient vers Beth-Jeschimoth; et du côté du midi, sur le pied du Pisga.
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 Og, roi de Basan, seul reste des Rephaïm, qui habitait à Aschtaroth et à Édréï.
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 Sa domination s’étendait sur la montagne de l’Hermon, sur Salca, sur tout Basan jusqu’à la frontière des Gueschuriens et des Maacathiens, et sur la moitié de Galaad, frontière de Sihon, roi de Hesbon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moïse, serviteur de l’Éternel, et les enfants d’Israël, les battirent; et Moïse, serviteur de l’Éternel, donna leur pays en possession aux Rubénites, aux Gadites, et à la moitié de la tribu de Manassé.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 Voici les rois que Josué et les enfants d’Israël battirent de ce côté-ci du Jourdain, à l’occident, depuis Baal-Gad dans la vallée du Liban jusqu’à la montagne nue qui s’élève vers Séir. Josué donna leur pays en possession aux tribus d’Israël, à chacune sa portion,
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 dans la montagne, dans la vallée, dans la plaine, sur les coteaux, dans le désert, et dans le midi; pays des Héthiens, des Amoréens, des Cananéens, des Phéréziens, des Héviens et des Jébusiens.
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 Le roi de Jéricho, un; le roi d’Aï, près de Béthel, un;
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 le roi de Jérusalem, un; le roi d’Hébron, un;
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 le roi de Jarmuth, un; le roi de Lakis, un;
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 le roi d’Églon, un; le roi de Guézer, un;
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 le roi de Debir, un; le roi de Guéder, un;
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 le roi de Horma, un; le roi d’Arad, un;
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 le roi de Libna, un; le roi d’Adullam, un;
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 le roi de Makkéda, un; le roi de Béthel, un;
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 le roi de Tappuach, un; le roi de Hépher, un;
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 le roi d’Aphek, un; le roi de Lascharon, un;
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 le roi de Madon, un; le roi de Hatsor, un;
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 le roi de Schimron-Meron, un; le roi d’Acschaph, un;
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 le roi de Taanac, un; le roi de Meguiddo, un;
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 le roi de Kédesch, un; le roi de Jokneam, au Carmel, un;
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 le roi de Dor, sur les hauteurs de Dor, un; le roi de Gojim, près de Guilgal, un;
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 le roi de Thirtsa, un. Total des rois: trente et un.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.