< Zacharie 1 >

1 Le huitième mois de la seconde année; sous Darius; la parole du Seigneur vint à Zacharie; fils de Barachie; fils d'Addo; le prophète; disant:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 Le Seigneur a été transporté d'un grand courroux contre vos pères.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 Et tu diras au peuple: Voici ce que dit le Seigneur tout-puissant: Convertissez-vous à Moi; dit le Seigneur des armées, et Je reviendrai à vous, dit le Seigneur des armées.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Et ne soyez pas comme vos pères, à qui les prophètes d'autrefois firent des reproches, disant: Voici ce que dit le Seigneur, Maître de toutes choses: Quittez vos mauvaises voies et vos œuvres criminelles; et ils n'écoutèrent pas, et ils ne s'empressèrent pas de M'obéir, dit le Seigneur.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Où sont vos pères? Où sont les prophètes? Est-ce qu'ils vivront toujours?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Accueillez donc Mes paroles et Mes ordonnances, et tout ce que par Mon Esprit J'ai intimé à Mes serviteurs les prophètes, qui ont repris vos pères; or ceux-ci ont répondu, et ont dit: le Seigneur nous a traités selon ce qu'Il avait résolu, et ainsi a-t-Il fait, à cause de nos voies et de nos œuvres.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Le vingt-quatrième jour du onzième mois, celui du Sabbat, la deuxième année du règne de Darius, la parole du Seigneur vint à Zacharie, fils de Barachie, fils d'Addo, le prophète, disant:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 J'ai eu la nuit une vision. Et voilà qu'un homme était monté sur un cheval fauve, et il se tenait entre des montagnes ombreuses, et il y avait derrière lui des chevaux roux, gris-pommelé, tachetés et blancs.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Et je dis: Qui sont ceux-là, Seigneur? Et l'ange qui parlait avec moi me dit: Je te montrerai ce que c'est.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 Et l'homme qui se tenait debout entre les montagnes, parla, et il me dit: Ceux-là sont ceux que le Seigneur a envoyés pour aller par toute la terre.
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 Et ils parlèrent à l'ange du Seigneur qui se tenait entre les montagnes, et ils dirent: Nous sommes allés par toute la terre, et voilà que toute la terre est habitée, et elle est en repos.
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 Et l'ange du Seigneur répondit: Seigneur tout-puissant, dit-il, jusques à quand seras-Tu sans miséricorde pour Jérusalem et pour les villes de Juda, que Tu as délaissées depuis soixante-dix ans?
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 Et le Seigneur tout-puissant répondit à l'ange qui parlait avec moi, et lui dit des paroles bonnes et consolantes;
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 et l'ange qui parlait avec moi me dit: Crie de toute ta force. Voilà ce que dit le Seigneur tout-puissant: Je suis pris d'un grand zèle pour Jérusalem et pour Sion;
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 mais J'ai une grande colère contre les gentils qui se sont coalisés; car Me voyant un peu irrité contre elle, ils se sont coalisés pour lui faire du mal.
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 C'est pourquoi voici ce que dit le Seigneur: Je reviendrai à Jérusalem en Ma miséricorde, et Mon temple y sera réédifié, dit le Seigneur tout-puissant; et il étendra encore le cordeau sur Jérusalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Et l'ange qui parlait avec moi ajouta: Crie encore de toute ta force: Voilà ce que dit le Seigneur Tout-Puissant: Leurs villes seront de nouveau remplies de biens, et le Seigneur sera miséricordieux envers Sion, et Jérusalem sera Son élue.
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Et je levai les yeux, et je regardai, et je vis quatre cornes.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 Et je dis à l'ange qui parlait avec moi: Qu'est cela, Seigneur? Et il me dit: Ce sont les cornes qui ont dispersé Juda, Israël et Jérusalem.
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Et le Seigneur me montra quatre ouvriers.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 Et je dis: Que vont faire ceux-ci? Et Il dit: Voilà les cornes qui ont dispersé Juda et brisé Israël, sans que nul ait levé la tête; or ceux-ci sont venus pour les aiguiser de leurs mains, et les quatre cornes sont les nations qui ont levé la corne contre la terre du Seigneur, pour disperser Mon peuple.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

< Zacharie 1 >