< Psaumes 72 >
1 Pour Salomon. Ô Dieu, donne au roi ton jugement, et au fils du roi ton équité
Ti Solomoni. Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run, ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
2 Pour juger ton peuple avec justice, et tes pauvres avec équité.
Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo, yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
3 Que les montagnes et les collines reçoivent la paix pour ton peuple.
Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
4 Il jugera avec justice les pauvres du peuple, et il sauvera les fils des pauvres, et il humiliera le calomniateur.
Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn yóò gba àwọn ọmọ aláìní; yóò sì fa àwọn aninilára ya.
5 Durant les générations des générations, il subsistera autant que le soleil et plus que la terre.
Àwọn òtòṣì àti aláìní yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn, yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
6 Il descendra comme la pluie sur une toison, et comme les gouttes de la rosée découlant sur la terre.
Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀, bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
7 En ses jours, la justice se lèvera avec la plénitude de la paix, et durera jusqu'à ce que la lune disparaisse.
Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà; títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
8 Et il régnera d'une mer à l'autre mer, et des fleuves aux limites de la terre habitable.
Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
9 Devant lui, les Éthiopiens se prosterneront, et ses ennemis lécheront la poussière.
Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
10 Les rois de Tharsis et les îles lui feront des présents; les rois des Arabes et de Saba lui apporteront leurs offrandes.
Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù wọn yóò mú ọrẹ wá fún un; àwọn ọba Ṣeba àti Seba wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
11 Et tous les rois l'adoreront, tous les peuples lui seront asservis,
Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
12 Parce qu'il aura protégé contre le puissant le pauvre et l'indigent, à qui nul n'était secourable.
Nítorí yóò gba àwọn aláìní nígbà tí ó bá ń ké, tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
13 Il épargnera le mendiant et le pauvre; il sauvera les âmes des indigents.
Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
14 Il affranchira leurs âmes de l'usure et de l'iniquité; leur nom sera en honneur devant lui.
Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
15 Et il vivra, et il lui sera donné de l'or de l'Arabie; perpétuellement on fera des vœux pour lui, et tout le jour on le bénira.
Yóò sì pẹ́ ní ayé! A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba. Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
16 Il sera l'appui de la terre jusqu'aux cimes des montagnes; ses fruits s'élèveront au-dessus du Liban, et des essaims sortiront de la cité, comme les herbes des champs.
Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀; ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
17 Que son nom soit béni dans tous les âges; son nom subsistera plus que le soleil; et en lui toutes les tribus de la terre seront bénies, toutes les nations célèbreront sa gloire.
Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé; orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó. Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
18 Béni soit le Seigneur Dieu d'Israël, qui seul fait des prodiges.
Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli, ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
19 Et béni soit son nom glorieux dans l'éternité et dans tous les siècles, et que toute la terre soit pleine de sa gloire. Ainsi soit-il, ainsi soit-il.
Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé; kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
20 Ici finissent les hymnes de David, fils de Jessé.
Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.