< Psaumes 33 >
1 De David. Justes, mettez votre joie dans le Seigneur; la louange convient aux cœurs droits.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Chantez sur la cithare les louanges du Seigneur; chantez pour lui sur la harpe à dix cordes.
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Chantez pour lui un cantique nouveau; chantez en accord et à haute voix.
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 Car la parole du Seigneur est sûre; il est fidèle en toutes ses œuvres.
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 Il aime la miséricorde et la justice; la terre est pleine de la miséricorde du Seigneur.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 Les cieux se sont affermis à la parole du Seigneur, et toute leur vertu au souffle de sa bouche.
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 Il a rassemblé comme dans une outre les eaux de la mer; il a déposé les abîmes dans ses trésors.
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Que toute la terre craigne le Seigneur; que ceux qui habitent le monde tremblent devant lui.
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 Car il a dit, et ils ont été; il a commandé, et ils ont été créés.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 Le Seigneur dissipe les conseils des nations; il réprouve les pensées des peuples; il réprouve les desseins des princes.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 Mais le conseil du Seigneur dure éternellement; les pensées de son cœur vivent de génération en génération.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 Heureuse la nation dont le Seigneur est le Dieu; heureux le peuple qu'il s'est choisi pour héritage.
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 Le Seigneur a regardé du ciel, il a vu tous les fils des hommes.
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 De la demeure qu'il s'est préparée, il regarde tous ceux qui habitent la terre.
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 C'est lui qui a formé le cœur de chacun d'eux; il connaît toutes leurs œuvres.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 Un roi n'est pas sauvé par une armée nombreuse; un géant ne sera pas délivré par sa grande force.
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 Le cheval trompe celui qui en attend le salut, et la multitude de ses forces ne le sauvera point.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 Voilà que les yeux du Seigneur sont sur ceux qui le craignent et qui espèrent en sa miséricorde;
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 Pour qu'il sauve leurs âmes de la mort, qu'il les nourrisse au temps de la famine.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 Notre âme attend le Seigneur; car il est notre protecteur et notre champion;
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 Car en lui notre cœur mettra sa joie, et nous avons espéré en son saint nom.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 Seigneur, répands sur nous ta miséricorde, autant que nous l'avons espéré de toi.
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.