< Psaumes 129 >

1 En Jérusalem. Souvent ils m'ont attaqué dès ma jeunesse; que maintenant Israël dise:
Orin fún ìgòkè. “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá,” jẹ́ kí Israẹli kí ó wí nísinsin yìí;
2 Souvent ils m'ont attaqué dès ma jeunesse, et ils n'ont rien pu sur moi.
“Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá; síbẹ̀ wọn kò tí ì borí mi.
3 Les pécheurs ont frappé sur mon dos; ils ont prolongé leur iniquité.
Àwọn awalẹ̀ walẹ̀ sí ẹ̀yìn mi: wọ́n sì la aporo wọn gígùn.
4 Le Seigneur en sa justice a brisé le cou des pécheurs.
Olódodo ni Olúwa: ó ti ké okùn àwọn ènìyàn búburú kúrò.”
5 Qu'ils soient confondus et mis en fuite, tous ceux qui haïssent Sion.
Kí gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni kí ó dààmú, kí wọn kí ó sì yí ẹ̀yìn padà.
6 Qu'ils deviennent comme l'herbe des toits, qui sèche avant d'être arrachée,
Kí wọn kí ó dàbí koríko orí ilẹ̀ tí ó gbẹ dànù kí ó tó dàgbàsókè,
7 Et qui ne remplit ni la main du faucheur ni le sein du botteleur.
èyí tí olóko pípa kó kún ọwọ́ rẹ̀: bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń di ìtí, kó kún apá rẹ̀.
8 Sur eux les passants n'ont point dit: Que la bénédiction du Seigneur soit avec tous; nous vous bénissons au nom du Seigneur.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń kọjá lọ kò wí pé, ìbùkún Olúwa kí ó pẹ̀lú yín: àwa ń súre fún yin ní orúkọ Olúwa.

< Psaumes 129 >