< Psaumes 11 >

1 Jusqu'à la Fin, psaume de David. Je me confie au Seigneur; comment dites- vous à mon âme: Fuyez sur la montagne, comme un passereau?
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
2 Car voici que les pécheurs ont tendu leur arc; la flèche est prête dans le carquois, afin de percer dans l'obscurité de la nuit les hommes au cœur droit.
Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
3 Ils ont détruit ce que tu as fait; mais le juste, qu'a-t-il fait?
Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
4 Le Seigneur réside en son temple saint; le Seigneur a son trône au ciel; ses yeux sont fixés sur le pauvre; ses regards interrogent les fils des hommes.
Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
5 Le Seigneur interroge le juste et l'impie; celui qui aime l'iniquité hait son âme.
Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
6 Il fera pleuvoir les pièges sur les pécheurs; le fer, le soufre, le vent d'orage, sont une part de leur calice.
Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
7 Car le Seigneur est juste, et il a toujours aimé la justice; sa face regarde l'équité.
Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.

< Psaumes 11 >