< Proverbes 31 >

1 Ces paroles de moi ont été dites par Dieu; elles sont l'oracle du roi que sa mère a instruit.
Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
2 Enfant, que garderas-tu? Quoi? La parole de Dieu. Mon fils premier-né, que me reste-t-il à te dire, enfant de mes entrailles, enfant de mes yeux?
“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi! Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3 Ne donne point aux femmes ta richesse, ta pensée et ta vie, de peur d'un remords tardif;
Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin, okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4 fais tout avec prudence; bois du vin avec mesure. Les princes sont irascibles; qu'ils ne boivent point de vin,
“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli, kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì, kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
5 de peur qu'en buvant ils n'oublient la sagesse, et ne puissent plus juger les pauvres avec droiture.
kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí, kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
6 Enivrez les affligés; donnez du vin à boire à ceux qui souffrent;
Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
7 afin qu'ils oublient leur pauvreté, et ne se souviennent plus de leurs peines.
Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8 Ouvre la bouche à la parole de Dieu, et rends justice à tous.
“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
9 Ouvre la bouche et juge selon l'équité, et plaide la cause du pauvre et du faible.
Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10 Une femme forte, qui la trouvera? Une telle femme a plus de prix que les pierres précieuses.
Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ.
11 Le cœur de son mari a confiance en elle; jamais une telle femme n'aura besoin de recourir aux riches dépouilles d'un ennemi.
Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12 Car elle emploie toute sa vie au bien de son époux.
Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13 Elle dévide le lin et la laine, et elle fait de ses mains d'utiles travaux.
Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14 Elle est comme un navire qui arrive de loin chargé de vivres;
Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
15 elle se lève avant le jour pour donner sa provende à la maison, et leur tâche à ses servantes.
Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16 Elle a considéré le champ, et l'a acheté; et, dans cette propriété, elle sème des graines que ses mains ont recueillies.
Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
17 Elle ceint fortement ses reins, et met à l'œuvre toute la force de ses bras.
Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
18 Elle sait par expérience que le travail est bon, et sa lampe ne s'éteint pas de toute la nuit.
Ó rí i pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
19 Elle étend les bras partout où il est utile, et ses mains ne quittent pas le fuseau.
Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
20 Elle a la main ouverte pour le pauvre, et présente un fruit au mendiant.
O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21 Son mari n'a pas à s'inquiéter des gens de sa maison, quel que soit le lieu où il est retenu; car elle a vêtu tous ceux qui sont auprès d'elle.
Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22 Elle a fait pour son mari des manteaux doubles, et pour elle-même des manteaux de fin lin et de pourpre.
Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
23 Son mari est considéré devant les portes de la ville, lorsqu'il siège au conseil avec les anciens de la terre.
A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
24 Elle fait des toiles de fin lin; elle vend des ceintures aux Chananéens.
Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
25 Elle ouvre la bouche avec prudence et mesure; elle a mis un frein à sa langue.
Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26 Elle s'est revêtue de force et de beauté, et goûte une douce joie dans ses derniers jours.
A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27 Les habitudes de sa maison sont réglées; elle ne mange point les fruits de la paresse.
Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
28 Elle ouvre la bouche sagement et selon la loi. Elle a élevé ses enfants avec tendresse, et ils se sont enrichis; et son époux a fait son éloge
Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
29 beaucoup de filles ont acquis des richesses, beaucoup ont été vertueuses; mais toi, tu es au-dessus d'elles, tu les as toutes surpassées.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
30 Les grâces sont trompeuses, et la beauté de la femme est vanité; mais la femme intelligente sera bénie, et celle qui craint le Seigneur sera louée.
Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.
31 Donnez-lui les fruits de ses lèvres, et que son époux soit loué aux portes de la ville.
Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

< Proverbes 31 >