< Michée 6 >
1 Écoutez donc la parole: Le Seigneur, le Seigneur a dit: Lève-toi, annonce le jugement aux montagnes, et que les collines entendent ta voix!
Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí: “Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá; sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèké gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.
2 Écoutez, montagnes, le jugement du Seigneur, et vous aussi, vallées, fondements de la terre; car le Seigneur vient en jugement devant Son peuple, et Il plaidera avec Israël.
“Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa; gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé. Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́; òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.
3 Mon peuple, que t'ai-Je fait? En quoi t'ai-Je contristé? En qui t'ai-Je déplu? Réponds-Moi.
“Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín? Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
4 Est-ce parce que Je t'ai fait sortir de la terre d'Égypte, que Je t'ai affranchi de la maison de servitude, et que J'ai envoyé devant toi Moïse, Aaron et Marie?
Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá. Mo rán Mose láti darí yín, bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
5 Mon peuple, souviens-toi donc de ce qu'a médité contre toi Balac, roi de Moab, et de la réponse que lui a rapportée Balaam, fils de Béor, depuis Sétim jusqu'à Galgala, afin que l'on connût la justice du Seigneur.
Ìwọ ènìyàn mi, rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn. Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali, kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”
6 Comment prendrai-je le Seigneur? Comment serai-je agréable à mon Dieu très-haut? Le prendrai-je par des holocaustes, par des veaux d'un an?
Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga? Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
7 Le Seigneur accueillera-t-Il des milliers de béliers, des myriades de chèvres grasses? Donnerai-je, pour mes impiétés, les premiers-nés de mes troupeaux, et, pour les péchés de mon âme, le fruit de mes entrailles?
Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò, tàbí sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìṣàn òróró? Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi, èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
8 Ô homme, faut-il te dire ce qui est bon? Est-ce que le Seigneur demande de toi quelque chose, sinon que tu pratiques la justice, que tu aimes la miséricorde, et que tu sois prêt à cheminer avec le Seigneur ton Dieu?
Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára, àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú, àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
9 La voix du Seigneur sera invoquée dans la ville, et sauvera ceux qui craignent Son Nom. Écoute, tribu: Qui donc mettra l'ordre en ta cité?
Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà, láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ. “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án.
10 Est-ce le feu? Est-ce la maison de l'impie amassant des trésors iniques, avec une insolente impiété?
Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀, àti òsùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
11 Sera-t-il absous, l'homme injuste avec ses fausses balances et ses faux poids en un sac?
Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́ pẹ̀lú òsùwọ̀n búburú, pẹ̀lú àpò òsùwọ̀n ẹ̀tàn?
12 Car c'est ainsi que ceux qui demeurent dans la ville ont amassé leurs richesses impies; et ils ne disent que des mensonges, et dans leur bouche leur langue s'est enorgueillie.
Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá; àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
13 Et Moi Je commencerai par te frapper, et Je t'effacerai à cause de tes crimes.
Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́, láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
14 Tu mangeras, et ne seras point rassasié, et il y aura sur toi des ténèbres; et le Seigneur Se détournera; tu ne seras point sauvée; et ceux qui échapperont seront livrés au glaive.
Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó; ìyàn yóò wà láàrín rẹ. Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu, nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
15 Tu sèmeras et ne moissonneras pas; tu pressureras l'olive, et tu ne seras pas oint de son huile; tu pressureras la grappe, et tu n'en boiras pas le vin; et les lois de Mon peuple seront abolies.
Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè ìwọ yóò tẹ olifi, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ; ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
16 Car tu as gardé les ordonnances de Zambri, et toutes les œuvres de la maison d'Achab; et tu as marché dans toutes leurs voies, pour que Je te livre, toi, à la destruction et aux sifflets de tes habitants; et vous recueillerez les opprobres des peuples.
Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́, àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu, tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn, nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà; ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”