< Michée 3 >

1 Et Il dira: Écoutez maintenant ces paroles, princes de la maison de Jacob, restes de la maison d'Israël; n'est-ce pas à vous de connaître le jugement?
Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
2 Ceux qui haïssent le bien et cherchent le mal, arrachent eux-mêmes la peau de leur corps et la chair de leurs os.
Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
3 De même qu'ils ont mangé mes chairs de Mon peuple, qu'ils l'ont écorché pour lui enlever la peau, qu'ils ont rompu ses os, qu'ils l'ont dépecé, comme les viandes qu'on fait cuire dans une marmite ou une chaudière
àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
4 de même ils crieront au Seigneur, et Il ne les écoutera pas; et en ce temps-là Il détournera d'eux sa face, parce qu'ils ont fait le mal en leurs pratiques contre le peuple.
Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
5 Voici ce que dit le Seigneur contre les prophètes qui égarent Mon peuple, qui mordent à pleines dents, qui lui annoncent la paix, et qui, si rien n'est donné à leur bouche, excitent la guerre contre lui:
Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
6 à cause de cela, la nuit sera pour vous sans visons, il y aura pour vous ténèbres sans prophéties; et le soleil se couchera sur les prophètes, et pour eux le jour sera obscurci.
Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
7 Et les voyants qui devinent les songes seront confondus, et les devins seront moqués, et tout le monde parlera contre eux, parce qu'il n'y aura personne pour les écouter.
Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
8 Pour moi, je me remplirai de force, inspiré par le Seigneur, par le jugement et l'autorité, pour faire connaître ses impiétés à Jacob et ses péchés à Israël.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
9 Écoutez donc ces paroles, chefs de la maison de Jacob, restes de la maison d'Israël, vous qui haïssez la justice et pervertissez toute droiture,
Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
10 qui bâtissez Sion dans le sang et Jérusalem dans l'iniquité.
tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
11 Les princes de Jérusalem ont jugé pour des présents; ses prêtres ont parlé pour un salaire; ses prophètes ont prédit pour de l'argent, et ils se sont reposés sur le Seigneur, disant: Est-ce que le Seigneur n'est pas avec nous? Jamais il ne nous arrivera malheur.
Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
12 À cause de cela, à cause de vous, la charrue passera sur Sion comme sur un champ; Jérusalem ressemblera à la cabane d'un garde de vergers, et la montagne du temple sera une forêt de chênes.
Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

< Michée 3 >