< Lamentations 5 >
1 Souvenez-vous, Seigneur, de ce qui nous est advenu; regardez et voyez notre opprobre.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Notre héritage est passé à un autre peuple, et nos demeures à des étrangers.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Nous sommes orphelins; notre père n'est plus; nos mères sont comme des veuves.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Nous avons bu de l'eau à prix d'argent; nous avons porté notre bois sur notre cou.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Nous avons été persécutés; nous avons travaillé et nous n'avons pas eu de relâche.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 L'Égypte nous a donné la main, Assur aussi, mais pour leur propre intérêt.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Nos pères ont péché, ils ne sont plus; nous avons porté leurs iniquités.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Des esclaves ont été nos maîtres, et il n'est pas de rédempteur pour nous tirer de leurs mains.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Nous apporterons notre pain pour nourrir nos âmes en face des glaives du désert.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Notre peau a été brûlée comme un four; elle a été contractée par les orages de la faim.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Ils ont outragé les femmes en Sion, et les vierges dans les villes de Juda.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Ils ont pendu de leurs mains les princes; ils n'ont point honoré les vieillards.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Les plus vaillants ont appris à pleurer, et les jeunes gens ont succombé sous le bois qu'ils portaient.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Et les vieillards ont cessé de siéger devant les portes; les plus habiles chanteurs ont cessé de chanter des psaumes.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 La joie a défailli dans notre âme; nos chœurs de danse se sont changés en deuil.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 La couronne est tombée de notre tête. Malheur à nous, parce que nous avons péché!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Et c'est pourquoi la douleur nous est venue; notre cœur a été contristé; nos yeux se sont couverts de ténèbres.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Les renards courent sur la Montagne de Sion, parce qu'elle est dépeuplée.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Mais vous, Seigneur, vous demeurez dans tous les siècles; votre trône subsistera de génération en génération.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Pourquoi, dans quel but nous oublierez-vous? Nous abandonnerez-vous aussi longtemps que dureront les jours?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Revenez à nous, Seigneur, et nous reviendrons à vous, et renouvelez pour nous les jours d'autrefois,
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Quoique vous nous ayez répudiés et que vous soyez violemment irrité contre nous.
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.