< Lamentations 2 >

1 Aleph. Comment le Seigneur, dans sa colère, a-t-il obscurci la fille de Sion? Il a précipité du ciel sur la terre la gloire d'Israël; il a oublié l'escabelle de ses pieds.
Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
2 Bath. Au jour de sa colère, le Seigneur a submergé la gloire d'Israël, et il ne l'a pas épargnée; il a détruit, dans sa colère, toute la beauté de Jacob; il a souillé son roi et ses princes.
Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
3 Ghimel. Dans sa colère, il a brisé tout le front d'Israël; il a détourné sa main droite, de la face de l'ennemi, et il a allumé dans Jacob comme un feu flamboyant, et il a tout dévoré alentour.
Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
4 Daleth. Il a tendu son arc, comme un ennemi menaçant; il a affermi sa main droite, comme un adversaire; et il a détruit tout ce qui la rendait belle à mes yeux; dans le tabernacle de la fille de Sion, il a répandu sa fureur, comme un fou.
Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
5 Hé. Le Seigneur est devenu comme un ennemi; il a submergé Israël; il a submergé ses édifices; il a renversé ses remparts, et il a multiplié les humiliations pour la ville de Juda.
Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
6 Vav. Et il a jeté çà et là son tabernacle, comme une vigne qu'on arrache; il a détruit ses fêtes. Le Seigneur a oublié ce qu'il avait fait en Sion pour les fêtes et le sabbat; et il a transpercé des grondements de sa colère le roi, le prêtre et le prince.
Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
7 Zaïn. Le Seigneur a répudié son autel, et il a ébranlé et renversé son sanctuaire; il a brisé, par la main de l'ennemi, les murs de son palais; des étrangers ont crié dans la maison du Seigneur, comme en un jour de fête.
Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
8 Cheth. Et le Seigneur a résolu d'abattre le rempart de la fille de Sion; il a tendu le cordeau; il n'a point détourné sa main que tout ne fût broyé; et l'avant-mur a pleuré, et le rempart partout à la fois s'est senti défaillir.
Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
9 Teth. Ses portes se sont enfoncées dans le sol; il a détruit et mis en pièces ses verrous; il a banni son roi et ses princes parmi les nations; et ses prophètes n'ont pas eu de vision envoyée par le Seigneur.
Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
10 Iod. Les vieillards de Sion se sont assis à terre; ils sont demeurés dans le silence; ils ont couvert de cendre leur tête; ils ont ceint des cilices; ils ont fait asseoir à terre les jeunes vierges de Jérusalem.
Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
11 Caph. Mes yeux se sont éteints dans les larmes, mon cœur est troublé, ma gloire s'est répandue à terre, à cause de l'affliction de la fille de mon peuple dans le temps que le petit enfant, et ceux encore à la mamelle, mouraient dans les rues de la ville.
Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
12 Lamed. Ils disaient à leurs mères: Où est le pain, où est le vin? dans le temps que dans les rues de la ville ils tombaient défaillants, comme des blessés à mort, et qu'ils rendaient l'âme sur le sein de leurs mères.
Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
13 Mem. Quel témoignage puis-je te rendre? qui puis-je comparer à toi, fille de Jérusalem? Qui te sauvera, qui te consolera, vierge fille de Sion? Le calice de ton affliction s'est agrandi; qui te guérira?
Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
14 Noun. Tes prophètes ont eu pour toi des visions vaines et folles, et ils ne t'ont point découvert ton iniquité, pour empêcher que tu ne sois captive, et ils ont eu pour toi des rêves de mensonge; ils t'ont vue poursuivant tes ennemis.
Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
15 Samech. Les passants, sur la voie, ont battu des mains; ils ont sifflé, ils ont secoué la tête sur la fille de Jérusalem. Ils ont dit: Est-ce là cette ville, couronne de joie sur toute la terre?
Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
16 Aïn. Tous tes ennemis ont ouvert la bouche contre toi; ils ont sifflé et grincé des dents, et ils ont dit: Dévorons-la. Sans doute, voici le jour que nous attendions, nous l'avons trouvé, nous l'avons vu.
Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
17 Phé. Le Seigneur a fait ce qu'il avait résolu; il a accompli sa parole; il a fait les choses qu'il avait commandées depuis les anciens jours; il a tout détruit, il n'a rien épargné, et il a fait de toi la joie de ton ennemi; et il a relevé le front de ton oppresseur.
Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
18 Tsadé. Leur cœur a crié au Seigneur; remparts de Sion, versez nuit et jour des larmes par torrents; ne te donne pas de relâche; que la prunelle de tes yeux ne soit pas muette.
Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
19 Coph. Lève-toi, réjouis-toi en Dieu; la nuit, pendant la première veille, épanche ton cœur, comme de l'eau, devant la face du Seigneur; élève vers lui les mains pour la vie de tes petits enfants, qui sont défaillants de faim à tous les coins de rue.
Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
20 Resch. Voyez, Seigneur, considérez à quel point vous nous avez vendangés. Des mères peuvent-elles manger le fruit de leurs entrailles? Jamais cuisinier a-t-il apprêté un bourgeon? Peut-on tuer des enfants à la mamelle? Peut-on, dans le sanctuaire, tuer le prêtre et le prophète?
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
21 Schin. L'enfant et le vieillard sont gisants dans la rue; mes vierges et mes jeunes hommes ont été emmenés captifs; vous avez tout tué par le glaive et par la faim. Au jour de votre colère, vous avez tout massacré, et vous n'avez rien épargné.
“Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
22 Thav. Le Seigneur a signalé un jour de fête pour tous mes ennemis d'alentour, le jour de sa colère; nul n'a été sauvé ni épargné, et c'est moi- même qui ai fortifié et multiplié tous mes ennemis.
“Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”

< Lamentations 2 >