< Juges 17 >
1 Il y avait, dans les montagnes d'Ephraïm, un homme qui se nommait Michas.
Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
2 Et il dit à sa mère: Les onze cents sicles d'argent que tu as pris pour toi, et au sujet desquels tu m'as adjuré avec des imprécations, en me disant: «Vois, l'argent est avec moi; » ces sicles, je les ai pris. Et sa mère répondit: Beni soit mon fils, au nom du Seigneur.
sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
3 Et il rendit à sa mère les onze cents sicles d'argent, et sa mère s'écria: J'ai consacré au Seigneur cet argent, qui passe de ma main en celle de mon fils, pour qu'on en fasse une sculpture et un ouvrage en fonte, et je te le remettrai tout à l'heure à cet effet.
Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
4 Et il rendit l'argent à sa mère, qui en prit deux cents sicles pour les donner à un orfèvre; celui-ci en fit une sculpture et un ouvrage en fonte; après quoi, ces images restèrent en la maison de Michas.
Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
5 La maison de Michas était pour lui la maison de Dieu; il fit un éphod, des théraphim, et il remplit la main de l'un de ses fils qui fut chez lui le prêtre.
Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
6 En ces jours-là, il n'y avait point de roi en Israël; chacun faisait ce qui était droit à ses yeux.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
7 Or, il y avait un jeune homme de Bethléem en Juda qui était lévite, et demeurait là.
Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
8 Cet homme, étant parti de Bethléem, ville de Juda, afin de demeurer en un autre lieu à son gré, atteignit les montagnes d'Ephraïm, et il trouva sur son chemin la maison de Michas.
ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
9 Et Michas lui dit: D'où viens-tu? Et il lui dit: Je suis lévite de Bethléem en Juda; je vais demeurer en un autre lieu à mon gré.
Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
10 Et Michas lui dit: Reste avec moi; sois pour moi un père et un prêtre, je te donnerai dix sicles par jour, avec des vêtements et ce qui sert à la vie.
Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
11 Le lévite entra donc; il commença à demeurer auprès de l'homme, et le jeune homme fut pour lui comme l'un de ses fils.
Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
12 Michas remplit la main du lévite; celui-ci fut chez lui le prêtre, et il fit partie de la maison de Michas.
Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
13 Alors, Michas dit: Je reconnais maintenant que le Seigneur me favorise, puisqu'un lévite est prêtre chez moi.
Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”