< Josué 12 >

1 Et voici les rois que firent disparaître les fils d'Israël, et dont la terre devint l'héritage de ces derniers au delà du Jourdain, sur la rive orientale, depuis le val d'Arnon jusqu'au mont Hermon (toute la terre d'Araba, à l'orient):
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Séhon, roi des Amorrhéens, qui demeurait en Esebon et régnait sur tout le pays, depuis Arnon qui est dans la vallée dont elle occupe une partie, et depuis le milieu de Galaad jusqu'à Jaboc, limite des fils d'Ammon,
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 Et sur Araba jusqu'à la rive orientale de la mer de Cénéroth, et jusqu'à la rive orientale de la mer d'Araba (la mer des Sels), vers la route d'Asimoth, à partir de Théman, qui est sous Asedoth-Phasga.
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 Et le roi de Basan, Og, reste des géants, qui habitait en Astaroth et en Edraïn, et
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 Régnait, depuis le mont Hermon et depuis Secchaï, sur toute la terre de Basan, jusqu'aux confins de Gergési, sur Machis et sur la moitié de Galaad, limitrophe de Séhon, roi d'Esebon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moïse, serviteur de Dieu, et les fils d'Israël détruisirent ces deux rois, et ils donnèrent leurs royaumes en héritage a Ruben, a Gad et à la demi-tribu de Manassé.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 Et voici les rois des Amorrhéens que détruisirent Josué et les fils Israël en deçà du Jourdain, du côté de l'occident, depuis Balagad, dans la plaine au- dessous du Liban, jusqu'aux montagnes de Chelcha qui s'élèvent vers Séir. Et Josué donna leurs royaumes en héritage aux tribus d'Israël en tirant les portions au sort.
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 Dans la montagne, et dans la plaine, et dans Araba, et dans Asedoth, et dans le désert, en Nageb, il détruisit l'Hettéen, l'Amorrhéen, le Chananéen, le Phérézéen, l'Evéen et le Jébuséen,
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 Le roi de Jéricho, le roi d'Haï qui est près de Béthel,
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 Le roi de Jérusalem, le roi d'Hébron,
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 Le roi de Jérimuth, le roi de Lachis,
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 Le roi d'Elam, le roi de Gazer,
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 Le roi de Dabir, le roi de Gader,
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 Le roi d'Hermath, le roi d'Ader,
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 Le roi de Lebna, le roi d'Odollam,
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 Le roi d'Elath,
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 Le roi de Taphut, le roi d'Opher,
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 Le roi d'Ophec d'Aroc,
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 le roi d'Aaom,
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 Le roi de Symoon, le roi de Mambroth, le roi d'Aziph,
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 Le roi de Cadès, le roi de Zachac,
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 Le roi de Maredoth, le roi de Jécom du mont Carmel,
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 Le roi d'Odollam de Phennéaldor, le roi de Géï en Galilée,
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 Le roi de Thersa; en tout: vingt-neuf rois.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.

< Josué 12 >