< Job 20 >

1 Et Sophar le Minéen dit:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 Ce n'est point de cette manière que je voudrais, sur ces choses, discuter avec toi; et vous tous vous ne vous y êtes pas mieux pris.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Je mettrai à profit ce que m'enseigne ma retenue, et l'esprit d'intelligence répondra pour moi.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Est-ce que l'on ne sait pas ces choses depuis que l'homme a été placé sur la terre?
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 Joie des méchants, chute extraordinaire; plaisir des pervers, ruine.
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Lors même que les présents de l'impie monteraient jusqu'au ciel, et que ses sacrifices atteindraient les nuées;
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 Lors même qu'il serait soutenu par de forts étais, finalement il périra, et ceux qui le connaissaient diront: Où est-il?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 On ne le voit non plus qu'un songe évanoui, et il s'est envolé comme une vision nocturne.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 L'œil a regardé et il n'est plus là, et le lieu qu'il habitait ne s'apercevra plus.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Que ses fils meurent sous les coups des petits; que ses mains ne connaissent plus que les douleurs.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Ses os ont eu la force de la jeunesse, et ils sont couchés comme lui dans la terre.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 Si la méchanceté est douce à sa bouche, il la cachera sous sa langue,
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 Il ne s'en fera pas faute, et il n'en laissera rien perdre; et il la fera descendre au fond de son gosier.
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 Mais elle ne lui profitera pas; ce sera en ses entrailles un venin d'aspic.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Il vomira sa richesse injustement acquise, et un ange l'expulsera de la maison où il l'aura amassée.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Puisse-t-il s'allaiter du fiel des dragons; puisse la langue des serpents le faire périr.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Qu'il ne voie plus de lait trait au pâturage; qu'il ne mange ni beurre ni miel.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Il s'est fatigué pour des choses vaines et insensées, pour des biens dont il ne goûtera pas, qui lui serviront comme un nerf desséché où il n'y a rien à manger ni à boire.
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Car il a brisé les demeures d'une multitude d'hommes puissants; il les a dépouillés de maisons qu'il n'avait point bâties.
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Il ne trouvera pas son salut dans ses trésors; il ne sera point sauvé par sa convoitise.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Jamais rien ne reste de ses aliments; aussi ses richesses pour lui ne porteront pas de fleurs.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 A peine à son repas se sera-t-il bien gorgé, qu'il sera oppressé et torturé par toutes sortes d'étreintes.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Si, n'importe comment, tu as rempli sa panse, c'est comme si tu avais fait tomber sur lui le poids de ta colère et des flots de douleurs.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Il n'est point à l'abri d'une main armée de fer, ni à l'épreuve d'une flèche d'airain.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Que le trait entre par sa bouche; que les éclairs sillonnent ses demeures. Que les épouvantements se promènent à ses côtés;
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Que les ténèbres autour de lui ne se dissipent jamais; que la flamme le dévore sans le consumer; que son hôte ruine sa maison.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Que le ciel dévoile ses péchés; que la terre s'élève contre lui.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Que sa famille enfin périsse et qu'il voie luire le jour de la colère.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Tel est le sort que le Seigneur réserve à l'impie; telle est la part de richesses que lui donnera Celui qui voit tout.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

< Job 20 >