< Jérémie 14 >
1 Et la parole du Seigneur vint à Jérémie au sujet de la sécheresse.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
2 La Judée a pleuré, et ses portes sont solitaires, et la terre est pleine de ténèbres, et un cri s'est élevé en Jérusalem.
“Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
3 Et les plus grands ont envoyé les plus petits puiser de l'eau. Ceux-ci sont allés aux puits; mais ils n'ont point trouvé d'eau, et ils sont revenus les cruches vides.
Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
4 Et les travaux de la terre ont péri, parce qu'il ne pleuvait pas; les laboureurs ont été confondus, et ils se sont voilé la tête;
Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
5 Et les biches ont mis bas dans la plaine, et elles ont abandonné leurs faons, parce qu'il n'y avait point d'herbe.
Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
6 Les ânes sauvages se sont arrêtés dans les vallons ombragés, et ils ont aspiré l'air; leurs yeux ont défailli, parce qu'il n'y avait point de fourrage.
Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
7 Nos péchés se sont élevés contre nous, Seigneur; prenez soin de nous à cause de vous-même; car nos péchés contre vous sont nombreux, c'est contre vous que nous avons péché.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
8 Seigneur, vous êtes l'espérance d'Israël; c'est vous qui sauvez au temps de l'affliction. Pourquoi êtes-vous devenu à notre égard comme un passager sur la terre, ou comme un indigène allant dans une hôtellerie.
Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
9 Serez-vous comme un homme endormi ou comme un homme impuissant à sauver? Vous êtes avec nous, Seigneur, et votre nom est le nom qui nous est donné; ne nous oubliez plus.
Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
10 Ainsi dit le Seigneur à ce peuple: Ils ont aimé à remuer leurs pieds, et ils n'y ont pas mis de mesure, et Dieu ne les a pas fait prospérer; maintenant il va se souvenir de leurs iniquités.
Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
11 Et le Seigneur me dit: Ne me prie pas en faveur de ce peuple pour le bénir.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
12 Car lors même qu'ils jeûneraient, je n'exaucerai point leur prière; et s'ils m'offrent des holocaustes et des victimes, je ne les agréerai point. Car moi, je les exterminerai par le glaive, la famine et la mort.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
13 Et je répondis: O vous, Seigneur vivant, voilà que leurs prophètes prophétisent, et disent: Vous ne verrez pas de glaive; il n'y aura pas de famine parmi vous; car je donnerai à cette terre et à ce lieu la vérité et la paix.
Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
14 Et le Seigneur me dit: Leurs prophètes prophétisent faussement en mon nom; je ne les ai point envoyés; je ne leur ai rien commandé; je ne leur ai rien dit. Ils vous prophétisent d'après des visions mensongères, des augures, des présages, des caprices de leur cœur.
Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
15 À cause de cela, dit le Seigneur, et pour ce qui regarde les prophètes qui prophétisent faussement en mon nom, et que je n'ai point envoyés, et qui disent: Il n'y aura en cette terre ni glaive ni famine, ces prophètes mourront d'une maladie cruelle, et ils seront consumés par la faim,
Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
16 Et le peuple pour qui ils prophétisent, gisant dans les rues de Jérusalem, périra par le glaive ou la famine; et nul n'ensevelira les morts, ni leurs femmes, ni leurs fils, ni leurs filles, et je ferai refluer sur eux leur propre méchanceté.
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
17 Et tu leur diras cette parole: Que vos yeux versent des larmes nuit et jour, et que vos pleurs ne s'arrêtent pas; car la fille de mon peuple a été écrasée et broyée, et sa blessure est pleine de douleurs.
“Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
18 Si je sors dans la plaine, voilà des cadavres frappés par le glaive; si je rentre dans la ville, voilà les horreurs de la famine, et le prêtre et le prophète sont allés en une terre qu'ils ne connaissaient pas.
Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
19 Est-ce que vous avez répudié Juda; et votre âme s'est-elle éloignée de Sion? Pourquoi nous avez-vous frappés, et n'y a-t-il pas pour nous de remède? Nous attendions la paix, et il n'est rien venu d'heureux; la guérison, et voilà le trouble.
Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
20 Nous reconnaissons nos péchés et les iniquités de nos pères; car c'est contre vous que nous avons péché.
Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
21 Cessez, en faveur de votre nom, de détruire le trône de votre gloire; souvenez-vous et ne rompez point votre alliance avec nous.
Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
22 Y a-t-il une seule idole des nations qui fasse tomber la pluie? Et si le ciel nous accorde ses largesses, n'est-ce point par vous? Aussi nous espérons en vous, Seigneur; car c'est vous qui avez fait toutes ces choses.
Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.